Èṣù jẹ́ ọ̀kan lára àwọn Òrìṣà tí àwọn ìran Yorùbá ń bọ. Ó wà lára àwọn òrìṣà tí Olódùmarè rán láti ìkọ̀lé ọ̀run wá sí ayé. Èṣù ni a lè pè ní olópàá tàbí agbófiró àwọn òrìṣà yòókù tí Olódùmarè rán. Ìdí nipé òun ní o máa rí i dájú pé wọ́n tèlé òfin.[1] Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé orúkọ Eṣù tí yàtọ̀ láti orílè-èdè kan sí òmíràn, ọ̀nà tí wọ́n ń gbà sìn í kò yàtọ̀.

A mask representing Eshu.

Ìgbàgbọ́ àtúnṣe

Àwọn orúkọ mìíràn tí wọ́n ń pe Èṣù ni Ẹlẹ́jẹ̀lú, Olúlànà, Ọbasìn, Láarúmọ̀, Ajọ́ńgọ́lọ̀, Ọba Ọ̀dàrà, Onílé Oríta, Ẹlẹ́gbára Ọ̀gọ, Olóògùn Àjíṣà, Láàlú Ògiri Òkò, Láàlù Bara Ẹlẹ́jọ́, Láaróyè Ẹbọra tí jẹ́ Látọpa.[2]

Èṣù jẹ́ alágbára, òrìṣà tó wúlò, bẹ́ẹ̀ sì ni o jẹ́ òrìṣà tó wà ní ibi gbogbo to bẹ́ẹ̀to jẹ́ pé nínú ọjọ́ mẹ́rin ti Yorùbá ní, gbogbo rẹ̀ ní wọ́n fi ń bọ Èṣù. Èyí yàtọ̀ sí àwọn òrìṣà mìíràn tó jẹ́ pé wọ́n máa ń ni ọjọ́ kan nínú ọ̀sẹ̀láti fi bo wọ́n, ọjọ́ gbogbo ni ti Èṣù Ọ̀darà".[3]

Wọ́n máa kí Èṣù báyìí A-bá-ni-wá-ọ̀ràn-bá-ò-rí-dá "'Onílé- oríta"' "'Láàlú"' "'Òkiri-oko"' àwọn oríkì tàbí orúkọ yìí fihàn irú ẹni tí Èṣù jẹ́. Oríta ní Èṣù máa ń gbé. Èṣù jẹ́ alárèékérékè èdá. Òun ni ó ń kọ́ àwọn ènìyàn láti máa pé ojú méjì ni gbogbo ọ̀rọ̀ máa ń ní. Ó máa ń ṣọ̀tún, ṣòsì má ba ìbìkan jẹ́, bẹ́ẹ̀ náà ni ó máa ń tọ́ni sọ́nà. Ìdí nì yìí tí wọ́n fi sọ pé Ẹ̀ṣù ṣe pàtàkì láti ní ayé tó létò.

Gg bí ohun tí Oluwo Aderemi Ifaoleepin Aderemi láti Ọ̀yọ́ Aláàfin, sọ, ó ní Èṣù Láàlù jẹ́ ẹ̀dá tó burú, tó kún fún ìkà, àrékérekè nígbà tí Láaróyè Ajọ́ńgọ́lọ̀ Ọkùnrin Òde jẹ́ ẹ̀dá tó dára, máa ń fẹ́ òtítọ àti ìwà Omolúàbí. Ìránṣẹ́ Olódùmarè nìkan kọ́ ni Èṣù jẹ́, óò máa ń jiṣẹ́ fún àwọn òrìṣà mìíràn. Bẹ́ẹ̀ náà ni ó jẹ́ alárinnà láàárín àwọn Ajogun àti àwọn èèyàn. Bẹ́ẹ̀ náà ni Èṣù lo wa nídìí gbígba ẹbọ àti pinpin ẹbọ fún àwọn  Ajogun.

Àwọn ìtọ́kasí àtúnṣe

  1. Falola, Toyin (March 2013). Esu: Yoruba God, Power, and the Imaginative Frontiers. Carolina Academic Press (June 24, 2013). ISBN 978-1611632224. 
  2. Fatunmbi, Awo Baba Falokun (June 1993). Esu-Elegba: Ifa and the Divine Messenger. Original Pubns (January 1, 1993). ISBN 978-0942272277. 
  3. Fatunmbi, Awo Baba Falokun (June 1993). Esu-Elegba: Ifa and the Divine Messenger. Original Pubns (January 1, 1993). ISBN 978-0942272277.