Achievers University jẹ́ ilé ẹ̀kọ́ gíga ifáfitì tí wọ́n tẹ̀dó sí ìlú Ọ̀wọ̀ ní ìpínlẹ̀ Oǹdó , lórílẹ̀ èdè Nàìjíríà

Yunifásitì Achievers
Established2007
TypeIfáfitì Aládàání
Vice-ChancellorOnímọ̀-ẹ̀rọ Ọ̀jọ̀gbọ́n T. S. Ìbíyẹmí
LocationÌlú Ọ̀wọ̀, Nàìjíríà
7°10′27″N 5°35′00″E / 7.174188°N 5.583249°E / 7.174188; 5.583249Coordinates: 7°10′27″N 5°35′00″E / 7.174188°N 5.583249°E / 7.174188; 5.583249
CampusÌlú-ńlá
Websitehttp://www.achievers.edu.ng

Ó jẹ́ ifáfitì Aládàání tí wọ́n dá sílẹ̀ lọ́dún 2017, tí Ìjọba Àpapọ̀ sìn fọwọ́ sí. Ó gúnwà sí àgbègbè Ìdásẹ̀n ní ìlú Ọ̀wọ̀. [1]

Ifáfitì Achievers University jẹ́ ọ̀kan lára ilé iṣẹ́ ẹ̀kọ́, the Achievers Group of Education and Training Organization, tí ó gúnwà sí ìlú Ìbàdàn ní ìpínlẹ̀ Ọ̀yọ́ lórílẹ̀-èdè Nàìjíríà. Ọ̀gbẹ́ni Bọ̀dé Ayọ̀rìndé àti àwọn onímọ̀ nípa ìkẹ́kọ̀ọ́ mìíràn ní wọ́n dá a sílẹ̀. Ifáfitì yìí bẹ̀rẹ̀ lọ́dún 2007 sí 2008. Àjọ tí ó ń ṣe kòkárí ètò ẹ̀kọ́ ifáfitì lórílẹ̀ èdè Nàìjíríà the Nigerian National University Commission kà á sí ipò mẹ́tàléláàádọ́ta nínú àwọn Ifáfitì tó pójúwọ̀n lórílẹ̀-èdè Nàìjíríà lọ́dún 2013.[2]

Àwọn Ìtọ́kasí àtúnṣe