Kọ́lá Òyéwọ̀ (tí wọ́n bí ní Ọjọ́ kẹtàdínlógbọ̀n oṣù kẹta ọdún 1946) jẹ́ àgbà òṣèré sinimá àgbéléwò àti olùkọ́ ilé ìwé Ifáfitì ọmọ orílẹ̀ èdè Nàìjíríà. Ó ti kópa nínú sinimá àgbéléwò lóríṣiríṣi. Sinimá kan gbòógì tó gbé ìràwọ̀ rẹ̀ jáde ní "Orogún Adédigba" Bí ó ṣe ń ṣiṣẹ́ tíátà náà ló ń ṣíṣe olùkọ́. Ó ti jẹ́ olùkọ́ ní ifáfitì Ọbáfẹ́mi Awolọ́wọ̀ tí wọ́n ń pè ní Obafemi Awolowo University, O.A.U., ní Ilé-Ifẹ̀, Redeemer's University, ní ìlú Ọ̀tà ní ìpínlẹ̀ Ògùn, bẹ́ẹ̀ náà ní Elizade University Ilara-Mokin, ní ìpínlẹ̀ Oǹdó.[1] [2] [3]

Ìgbà èwe àti aáyan ìkẹ́kọ̀ọ́ rẹ̀ àtúnṣe

Wọ́n bí Olóyè Kọ́lá Òyéwọ̀ sí ìlú Ọ̀bà-Ilé ni ìpínlẹ̀ Ọ̀ṣun lỌjọ́ kẹtàdínlógbọ̀n oṣù kẹta ọdún 1946. Àkọsílẹ̀ nípa ẹ̀kọ́ ìgbà èwe rẹ̀ farasin, ṣùgbọ́n ó kàwé gboyè nínú iṣẹ́ tíátà àti lítíréṣọ̀ a lóhùn èdè Yorùbá ní ifáfitì Ọbáfẹ́mi Awolọ́wọ̀ ní Ilé-Ifẹ̀ lọ́dún 1995. Ó tẹ̀ síwájú ní ifáfitì ìlú Ìbàdàn níbi tí ó ti kàwé gboyè dìgírì kejì àti oyè ọ̀mọ̀wé dọ́kítà nínú iṣẹ́ tíátà.[4]

Àtòjọ àwọn sinimá àgbéléwò tí Kọ́lá Òyéwọ̀ tí kópa àtúnṣe

  • Sango (1997)
  • Super Story (episode 1)
  • The Gods Are Not To Blame
  • Saworo Ide
  • Koseegbe (1995 [5]

Àwọn Ìtọ́kasí àtúnṣe

  1. "Kola Oyewo biography, net worth, age, family, contact & picture". Nigeria Business Directory - Find Companies, People & Places in Nigeria. 1946-03-27. Retrieved 2019-11-29. 
  2. "Kola Oyewo Archives - Nigeria and World News". The Guardian Nigeria News - Nigeria and World News. Retrieved 2019-11-29. [Ìjápọ̀ tí kò ṣiṣẹ́ mọ́]
  3. "Veteran actor, Kola Oyewo is 70 years old today - Nigerian Entertainment Today". Nigerian Entertainment Today. 2016-03-27. Retrieved 2019-11-29. 
  4. Julius-Adeoye, Rantimi (2015-08-03). "The Actor and the Character: A Study of Kola Oyewo As James Adubi in Family Ties". The Stage and The Screen: Perspective on Arts Production in Contemporary Nigeria. https://www.academia.edu/40956603/The_Actor_and_the_Character_A_Study_of_Kola_Oyewo_As_James_Adubi_in_Family_Ties. Retrieved 2019-11-29. 
  5. "Kola Oyewo". MUBI. Retrieved 2019-11-29.