Ngozi Ezeonu tí orúkọ àbísọ rẹ̀ ń jẹ́ Ngozi Ikpelue ni wọ́n bí ní Ọjọ́ kẹtàlélógún oṣù karùn-ún ọdún 1965 (May 23rd 1965) jẹ́ gbajúmọ̀ òṣèrébìnrin sinimá àgbéléwò àti akọ́ṣẹ́mọṣẹ́ òníròyìn tẹ́lẹ̀ ọmọ orílẹ̀-èdè Nàìjíríà. Ó jẹ́ gbajúmọ̀ òṣèrébìnrin ìlúmọ̀ọ́kà nípa ṣíṣe ẹ̀dá-ìtàn Ìyá nínú sinimá àgbéléwò lédè Gẹ̀ẹ́sì àti Ìgbò. [1][2][3] Lọ́dún 2012, ó kópa nínú sinimá àgbéléwò kan tí àkọ́lé rẹ̀ ń jẹ́ Adesuwa, èyí ló mú un gba àmìn ẹ̀yẹ Akádẹ́mì nínú sinimá gẹ́gẹ́ bí òṣèrébìnrin tó dára jùlọ níbi ayẹyẹ igbàmìẹ̀ẹ ẹlẹ́ẹ̀kẹjọ 8th Africa Movie Academy Awards.

Ngozi Ezeonu
Ngozi Ezeonu In "Family Secret", 2016
Ọjọ́ìbíNgozi Ikpelue
Ọjọ́ kẹtàlélógún oṣù karùn-ún ọdún 1965
ìlú Owerri
Orílẹ̀-èdèỌmọ Nàìjíríà
Iléẹ̀kọ́ gígaNigerian Institute of Journalism
Iṣẹ́Òṣèrébìnrin

Ìgbà èwe rẹ̀ àtúnṣe

Wọ́n bí ní Ngozi Ezeonu ní ìlú Owerri. Kí ó tó di gbajúmọ̀ òṣèré ìlúmọ̀ọ́kà, ó kàwé gbàwé ẹ̀rí nínú ìmọ̀ iṣẹ́ ìròyìn ní Nigerian Institute of Journalism, ó sìn ṣiṣẹ́ ní Radio Lagos àti Eko FM.[4]

Aáyan rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí òṣèré sinimá àgbéléwò àtúnṣe

Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ó gbajúmọ̀ gẹ́gẹ́ bí kíkópa ẹ̀dá-ìtàn ìyá, ó ti kọ́kọ́ kópa gẹ́gẹ́ bí ẹ̀dá-ìtàn ọlọ́mọgé ní ìbẹ̀rẹ̀ iṣẹ́ tíátà rẹ̀ ṣíṣe. Lọ́dún 1993, ni gbajúgbajà olùdarí sinimá-àgbéléwò nì, Zeb Ejiro fún ní ipa amúgbálẹ́gbẹ̀ẹ́ ẹ̀dá-ìtàn, tí ó pè ní Nkechi nínú sinimá àgbéléwò kan lédè Ìgbò, tí àkọ́lé rẹ̀ ń jẹ́ Nneka The Pretty Serpent. Lẹ́yìn èyí, ó kópa nínú sinimá àgbéléwò mìíràn tí wọ́n pe àkọ́lé rẹ̀ ní Glamour Girls lọ́dún 1994, ó kópa gẹ́gẹ́ bí ẹ̀dá-ìtàn tí wọ́n pè ní .[5]

Àtòjọ díẹ̀ lára àwọn sinimá-àgbéléwò rẹ̀ àtúnṣe

Ngozi tí kópa nínú sinimá àgbéléwò tí ó ju àádọ́jọ lọ, lára wọn ni;

  • Glamour Girls
  • Shattered Mirror
  • The Pretty Serpent
  • Tears of a Prince
  • Cry of a Virgin
  • Abuja Top Ladies
  • Family Secret
  • The Confessor
  • The Kings and Gods
  • Zenith of Sacrifice
  • A Drop of Blood
  • Divided Kingdom
  • Diamond Kingdom
  • God of Justice

Àwọn Ìtọ́kasí àtúnṣe