Salma Phillips jẹ́ Atọ́kùn ètò tẹlifíṣàn, oǹkọ̀wé àti olóòtú ètò láti ìlà-oòrùn Nàìjíríà. Àpèjá orúkọ rẹ̀ ni Ummu Salma Nabila Phillips. Ó gbajúmọ̀ gẹ́gẹ́ bí Atọ́kùn ètò lórí àwọn ìkànnì tẹlifíṣàn lápá ìlà-oòrùn Nàìjíríà.She is popularly known as the face of northern television.[1]Ó kàwé gbàwé ẹri dípólómà láti University of Jos, ní Nàìjíríà àti ìwé ẹ̀rí BSc. nínú ìmọ̀ òfin láti Rivers State University of Science and Technology, ní Port Harcourt. Àlá ayé rẹ̀ ní láti jẹ́ oníròyìn fún CNN.

Salma Phillips
Ọjọ́ ìbí31 August 1984
Nàìjíríà
Iṣẹ́Atọ́kùn ètò tẹlifíṣàn , oǹkọ̀wé.
Ọmọ orílẹ̀-èdèNàìjíríà
Notable worksThe Salma Show

Ìbẹ̀rẹ̀ rẹ̀ àtúnṣe

Salma jẹ́ àmúlùmálà ẹ̀yàFulani àti Calabari láti apá àríwá Nàìjíríà, ó sìn fẹ́ràn orin tàkasúfèé.[2]

Iṣẹ́ rẹ̀ àtúnṣe

Salma kàwé gbàwé ẹri dípólómà láti University of Jos, ní Nàìjíríà àti ìwé ẹ̀rí BSc. nínú ìmọ̀ òfin láti Rivers State University of Science and Technology, ní Port Harcourt. Salma àti gbajúgbajà olórin ọmọ Nàìjíríà, Aṣa, dìjọ lọ sí ilé-ìwé kọ́lẹ́ẹ̀jì kan náà.[2] Lọ́jọ́ keje oṣù kejì ọdún 2016,ó bẹ̀rẹ̀ ètò orí tẹlifíṣàn tí ó pè ní Salma Show, ètò tó dá lórí ọ̀rọ̀ tó ń lọ láwùjọ.[3] Lára àwọn aláwòkọ́ṣe rẹ̀, gẹ́gẹ́ bí ó ti sọ ni : Oprah Winfrey, Christian Amanpour, Funmi Iyanda àti Femi Oke.[4]

Àwọn ìtọ́kasí àtúnṣe

  1. The Editor. "Salma Phillips: The face of northern television". The Guardian. Retrieved 5 September 2016. 
  2. 2.0 2.1 "15 interesting things you didn't know about Salma Phillips.". Cosmopolitan. Retrieved 5 September 2016. 
  3. Bella Naija.com. "Watch "The Salma Show" today! Meet Salma Phillips, TV's New Northern Star". Bella Naija. Retrieved 5 September 2016. 
  4. Princess Irede Abumere. "Northern TV presenter to host "The Salma Show"". Pulse.ng. Retrieved 5 September 2016.