Pete Edochie: Ìyàtọ̀ láàrin àwọn àtúnyẹ̀wò
Content deleted Content added
Macdanpets (ọ̀rọ̀ | àfikún) New Page Àwọn àlẹ̀mọ́: Àtúnṣe ojú fóónù Àtúnṣe ojú fóónù Advanced mobile edit |
Macdanpets (ọ̀rọ̀ | àfikún) No edit summary Àwọn àlẹ̀mọ́: Àtúnṣe ojú fóónù Àtúnṣe ojú fóónù Advanced mobile edit |
||
Ìlà 1:
Oloye Pete Edochie, MON (tí wọ́n bí ní Ọjọ́ keje oṣù kẹta ọdún 1947) jẹ́ àgbà-ọ̀jẹ̀, gbajúmọ̀ àti ìlúmọ̀ọ́kà òṣèré sinimá àgbéléwò ọmọ orílẹ̀-èdè Nàìjíríà. Wọ́n kà á sí àgbà òṣèré sinimá-àgbéléwò tó lẹ́bùn eré sinimá ṣíṣe jùlọ nílẹ̀ adúláwọ̀ Áfíríkà. Èyí hànde látàrí onírúurú àmìn ẹ̀yẹ tí ó ti gbà gẹ́gẹ́ bí òṣèré sinimá àgbéléwò, pàápàá jùlọ àmìn ẹ̀yẹ láti ọwọ́ African Magic àti Africa Film Academy. Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé akọ̀ṣẹ́mọṣẹ́ olùṣàkóso àti gbajúgbajà agbóhùnsáfẹ́fẹ́ ni, ó di ìlúmọ̀ọ́kà òṣèré lọ́dún 1980 nígbà tí ó kópa gẹ́gẹ́ bí olú-ẹ̀dá ìtàn tí wọ́n pè ní Okonkwo nínú ìwé ìtàn àròsọ kan, Things Fall Apart tí àgbà-ọ̀jẹ̀ òǹkọ̀wé, Chinua Achebe kọ, tí wọ́n sọ di eré àgbéléwò orí ẹ̀rọ tẹlifíṣọ̀n NTA tó gbajúmọ̀ jùlọ nígbà náà. Gbajúmọ̀ Edochie pọ̀ tó bẹ́ẹ̀ gẹ́ tí Ààrẹ àná, Olúṣẹ́gun Ọbásanjọ́ fi dá a lọlá pẹ̀lú àmìn ẹ̀yẹ orílẹ̀ èdè Nàìjíríà, Member of the Order of the Niger, MON. Pete Edochie jẹ́ ọmọ ìjọ àgùdà.
|