Àlàdé Arómirẹ́: Ìyàtọ̀ láàrin àwọn àtúnyẹ̀wò

Content deleted Content added
Ṣ'èdá ojúewé pẹ̀lú "'''Muyideen Agboọlá Àlàdé Arómirẹ́''' tí gbogbo ènìyàn tún mọ̀ sí '''Àlàdé Arómirẹ́''' tí wọ́n bí ní Ìpínlẹ̀ Èkó ní..."
(Kò ní yàtọ̀)

Àtúnyẹ̀wò ní 22:13, 29 Oṣù Kẹ̀wá 2020

Muyideen Agboọlá Àlàdé Arómirẹ́ tí gbogbo ènìyàn tún mọ̀ sí Àlàdé Arómirẹ́ tí wọ́n bí ní Ìpínlẹ̀ Èkó ní ọjọ́ Kẹtàlá oṣù Kẹjọ ọdún 1963 jẹ́ gbajú-gbajà òṣèré ìtàgé, agbéré-jáde, àti ònkọ̀tàn ọmọ orílẹ̀-èdè Nàìjíríà.[1]

Ètò-ẹ̀kọ́ rẹ̀

Àlàdé lọ sí ilé-ẹ̀kọ́ alákọ̀ọ́bẹ̀rẹ̀ ti Ansar-ud-Deen tí ó wà ní Alakoso ní Ìpínlẹ̀ Èkó, tí ó sì lọ sí ilé-ẹ̀kọ́ girama ti Ansar-ud-Deen College, ní Ìlú Ìsọlọ̀ ní Ìpínlẹ̀ Èkó kan náà. Ó tún kọ́ ẹ̀kọ́ nípa eré oníṣẹ́ ní School of Arts rí ó wà ní Apapa.

Iṣẹ́ rẹ̀

Gẹ́gẹ́ bí òṣèré, ó ti rí gbogbo rògbàdìyàn àti akitiyan tí ó wà nínú lílo ìlànà "atabloid" tí àwọn àgbà òṣèré bíi: Moses Adéjùmọ̀, Olóyè Hubert Ògúndé ń lò láti gbé eré jáde tí ó sì ń ná wọn lówó gegere kí eré náà ó tó jáde síta fún àwọn ènìyàn. Ó dá ṣíṣe yíya eré sinimá àgbéléwò àkókọ́ sílẹ̀ tí ó pe àkọọ́lé rẹ̀ ní Ẹkùn ní ọdún 1989.[2]

  1. "Meet Alade Aromire, The Man Who Changed The Face Of Yoruba Movies And How He Died 11 Years Ago". City People Magazine. 2019-05-15. Retrieved 2020-10-29. 
  2. "I STARTED NOLLYWOOD...ALADE AROMIRE". Modern Ghana. 2007-10-01. Retrieved 2020-10-29.