Olusegun Mimiko

Olóṣèlú

Olusegun Mimiko jẹ olósèlú ọmọ ilẹ̀ Nàíjíríà àti Gómìnà Ìpínlẹ̀ Òǹdó láti ọdún 2009 dé ọdún 2017. Ọjọ́ kẹ́ta oṣù Ọ̀wàwà ní wọ́n bí Olúṣẹ́gun Rahman Mimiko ọdún 1954. Ó jẹ́ olùdíje fún ipò sẹ́nẹ́tọ̀ ní agbègbè àárín gbìngbùn Òǹdó lábẹ́ ẹgbẹ́ òṣèlú Zenith Labour Party nínú ìdìbò tó wáyé ní ìpínlẹ̀ Òǹdó.[1]

Olusegun Rahman Mimiko
Gomina Ipinle Ondo
Lọ́wọ́lọ́wọ́
Ó gun orí àga
24 February 2009
AsíwájúOlusegun Agagu
Àwọn àlàyé onítòhún
Ọjọ́ìbí3 Oṣù Kẹ̀wá 1954 (1954-10-03) (ọmọ ọdún 69)
Ẹgbẹ́ olóṣèlúLabour Party
(Àwọn) olólùfẹ́Olukemi Mimiko
Occupationphysician

Olúṣẹ́gun ní gómìnà alágbádá ẹlẹ́ẹ̀karùn-ún ní ìpínlẹ̀ Òǹdó, ní orílẹ̀-èdè Nàíjíríà láti 2009 sí 1017. Mimiko ti fi ìgbà kan jẹ́ mínísítà ìjọba àpapọ̀ fún ilé àti ìdàgbàsókè ìgbèríko, sẹ́kétírì sí ìjọba ìpínlẹ̀ Ondo, bẹ́ẹ̀ náà ni ó jẹ́ gómìnà àkọ́kọ́ tí ó jẹ lábẹ́ ẹgbẹ́ òṣèlú Labour party ní orílẹ̀-èdè Nàíjírià. Bákannáà ni ó jẹ komíṣọ́nà léèmejì fún ètò ìlera.

Ìlú Ondo ní ìpínlẹ̀ Ondo, apá Ìwọ̀-oòrù̀n gúsù orílẹ̀-èdè Nigeria. Àti kékeré ni ó ti nífẹ̀ẹ́ si òṣèlú, èyí sì farahàn nínú àwọn ipò tí ó dì mú nìgbà tí oh wà ní ilé-ìwé àwọn oníṣègùn òyìnbó ní University of Ife (tó di Obafemi Awolowo University lónìí).

Lẹ́yìn ìgbà tí ó parí agùnbánirọ̀, ó bẹ̀rẹ̀ sí ní ṣiṣẹ́ oníṣègùn òyìnbó. Ní ọdún 1985, ó dá ilé-iṣẹ́ MONA MEDICLINIC sílẹ̀ ní Ondo èyí ti ó dúró gẹ́gẹ́ bí ohun ètò ọ̀fẹ́ fún àgbègbè náà.[2]

Itokasi àtúnṣe