Ìfini ṣòwò nàbì (Sex Trafficking in Nigeria)

Ìkóniṣòwò nàbì ní orílẹ̀-èdè Nàìjíríà jẹ́ ọ̀nà kan tí wọ́n fi ń kóni rìnrìn-àjò fini ṣòwò nàbì lọ́nà àìtọ́ ní orílẹ̀-èdè Nàìjíríà. Ìkóni ṣòwò nàbì yi tun jẹ́ ọ̀nà ìfini ṣè òwò ẹrú ìgbàlódé (TIP) ní orílẹ̀-èdè Nàìjíríà. Fí fini ṣòwò nàbì lọ́nà àìtọ́ yí ma ń mú ìpálára àti aburú tó pọ̀ wà fún ẹni tí a mu ṣòwò yìí#, ẹbí rẹ̀ àti àwùjọ̀ rẹ̀ gbogbo. Ìkọ́ni rìnrìn-àjò lọ́nà àìtọ́ ma ń sábà dá lórí ìyanijẹ, ìrẹ́nijẹ, íṣẹrú àti ìfipá-múni ṣe ohun àìtọ́, pàá pàá jùlọ fífí àwọn ènìyàn tí wọ̀n bá kó rìnrìn àjò lọ́nà àìtọ́ náà ṣe òwò nàbì tí kò wá láti ọkàn wọn.

Àwọn aṣẹ́wo tí wọ́n dúró síwájú ilé-ọtí gogo ni Pattaya, Thailand
Ìfini ṣòwò nàbì (Sex Trafficking in Nigeria)
sex trafficking by country or territory
orílè-èdèNàìjíríà Àtúnṣe


Gẹ́gẹ́ bí òfin Trafficking Victims Protection Act of 2000 ṣe ṣe àpèjúwe rẹ̀, ni ó jẹ́ Ìgbanisíṣẹ́, ìgbanimọ́ra, ìpèsè fúnni, ìfipá múni, lọ́nà àti fífini ṣòwò nàbì lọ́nà àìtọ́ tí kò sí tọkàn ẹni wá, bí ó tilẹ̀ jẹ́ wípé ìbálòpọ̀ ipá tàbí ìfiniṣòwò nàbì pẹ̀lú awọ ọmọdé tí ọjọ́ orí wọn kò tíì tó ọdún méjìdínlógún ni a lè pè ní íkóni rìnrìn-àjò lọ́nà àìtọ́.[1]

Ní orílẹ̀-èdè Nàìjíríà, àwọn ọmọdékùnrin àti áwọn ọmọdébìnrin ni wọ́n ma ń kó rìnrìn-àjò lọ́nà àìtọ́ ní kẹ̀tí-kẹ̀tì láti orílẹ̀-èdè wọn lọ sí àwọn orílẹ̀-èdè bíi: Italy Saudi Arabia, North Africa, Europe, Faransé, Spain, Netherlands, Belgium, Austria, Norway,Amẹ́ríkà àti Asia fún òwò nàbì. Bákan náà ní wọ́n tùn ń ko àwọn ọmọdékùnrin àti àwọn ọmọdébìnrin tó fi mọ àwọn ọkùnrin àti obìnrin tí wọ́n jẹ́ abilékọ rìnrìn-àjò lọ sí àwọn ìlú àti orílẹ̀-èdè tí ó wà ní ìtòsí orílẹ̀-èdè Nàìjíríà Chad, Niger Republic, Benin Republic, Togo àti Ghana fún báárà ṣíṣe, òwò nàbì, iṣẹ́ ọmọ-ọ̀dọ̀, àti bẹ́ẹ̀ bẹ́ẹ̀ lọ. Iye áwọn ènìyàn tí wọ́n ń kó rìnrìn-àjò kúrò lọ́nà àìtọ́ ní orílẹ̀-èdè Nàìjíríà láàrín ọdún kan ma ǹ tó àádọ́talélẹ́ẹ̀dẹ́gbẹ̀rin (750,000) níye, nígbà tí wọ́n ń kó ìdá tí ò lé ní àádọ́rin (75%) nínu wọn rìnrìn-àjò láàrì́n orílẹ̀-èdè náà, bákan náà ni ìdá mẹ́tàlélógún (23%) ni wọn ń ipinle kọọkan, nigba ti wọn n ko ida meji ninu wọn jade kuro ni orilẹ-ede Naijiria laarin ọdun kan.[2]

Àwọn Ìtọ́kasí àtúnṣe

  1. "Sex Trafficking - Sexual Violence - Violence Prevention - Injury Center". CDC (in Èdè Sípáníìṣì). 2018-04-12. Retrieved 2022-03-30. 
  2. "Prevention of human trafficking". United Nations Office on Drugs and Crime. 2010-09-14. Archived from the original on 2022-04-15. Retrieved 2022-03-30. 

Àdàkọ:Cattergory: Human Trafficking in Nigeria