Ìlú Igbó-Ọrà
Ìlú Igbó-Ọrà Ojú-ìwé 13. àtúnṣe
Ìdèrè jẹ́ ìlú pàtàkì,
Tó ṣe kókó gan-an ní Bàràpá;
Tó jẹ́ ẹ̀yà Oòduà kan.
Ẹ̀gàn àtàwàdà ni wọ́n ń sọ̀rọ̀ “ọ̀bọ Ìdèrè”.
Kò mà mà sọ́bọ ní Dèrè ní pàtó,
Ìlú Ìdèrè Ojú-ìwé 14-16. àtúnṣe
Ayétẹ̀ jẹ́ ìlú pàtàkì,
Tó dúró gedegbe ni Bàràpá;
Tó jẹ́ ìlú olóríire.
Ayé, ìyá Onídèrè àkọ́kọ́,
Ṣóun ló tẹ̀ lú yìí dó;
Ìlú Ayétẹ̀ Ojú-ìwé 17. àtúnṣe
Kò sẹ́ni tí ò níí kú,
Kò sẹ́ni tí ò níí rọ̀run.
Ẹ jọ̀wọ́ ẹ má fi kú yọ̀ wá;
Gbogbo wa la sá jọ ń lọ.
Ẹní bá wáá fẹ́ kó yá,
Ìlú Tápà ní Ìbàràpá Ojú-ìwé 18. àtúnṣe
Ẹ tẹ́tí ẹ gbọ́n ná, jànmán-àn mi,
Ìrọra àtòkèwá lèmí fẹ́;
N ò fówó lásán;
Ìrọra lèmí fẹ́, n ò foníjàngbàn àlejò.
Nítorí bí “Agbọ́nmi ti í wó lé ẹja”,
Ọjàa Wàràwàrà Ojú-ìwé 19-20. àtúnṣe
Kò sẹ́ni tí ò níí kù,
Kò sẹ́ni tí ò níí rọ̀run.
Ẹ jọ̀wọ́ ẹ má fi kú yọ̀ wá;
Gbogbo wa la sá jọ ń lọ.
Ẹní bá wáá fẹ́ kó yá,
Ìrọra Àtòkèwá Ojú-ìwé 21. àtúnṣe
Ẹ tẹ́tí ẹ gbọ́ ná, jànmán-àn mi,
Ìrọra àtòkèwá lèmí fẹ́;
N ò fówó lásán;
Ìrọra lèmí fẹ́, n ò foníjàngbàn àlejò.
Nítorí bí “Agbọ́nmi ti í wó lé ẹja”,
Tí “Apàjùbà í bal é àpáròó jẹ́”;
Tí “Olùgbóńgbó tìǹlà í ṣẹ́gun ògúlúǹtu”;
Bí Àlá Ojú-ìwé 22. àtúnṣe
Bí àlá ni gbogbo ayé rí,
Bí òjìjìji ni gbogbo afẹ́ ayée wa.
Ṣùgbọ́n kì í ṣòfifo.
Bẹ́ẹ ni kì í ṣòfìfo.
Wíwá-ọlà-nínúu-làálàá,
Ọ̀gẹ̀dẹ̀ Ayé Ojú-ìwé 23. àtúnṣe
Bọ́gẹ̀dẹ̀ ayé ti ń bàjẹ́ bẹ́ẹ̀ ló ń pọ́n,
Báṣọ ayé ṣe ń gbó bẹ́ẹ̀ ló ń tàn.
Bá a bá rántíi kú,
La máa ń sinmi aré-sísá,
Àsìkò tá a bá rọ̀nà ọ̀run wò,
Gba Tìrẹ Ojú-ìwé 24. àtúnṣe
Kó sẹ́ni tí ó fi ọ́ ṣe yẹ̀yẹ́,
Tó o bá gba ohun tÓlú pè ní tìrẹ.
Taa ha lẹni tí ó fi ọ́ ṣẹ̀fẹ̀?
Bó o bá gba hun tÓrí pè lẹ́rùu rẹ?
Kò sẹ́ni tó jẹ́ fi ọ́ pòṣé,
Tó o bá gba hun tó dé bá ọ.
Ogun ńlá Ojú-ìwé 25. àtúnṣe
Ogun ńlá kan ń ṣẹlẹ̀ látàrí,
Tó jé isó gidi.
Àní isó inú ẹ̀kú,
Tó jẹ́ àramọ́ra gidi.
Èyí-ó-wù-mí-ò-wù-ọ́,
Èyí-ó-wù-ọ́-ò-wú-mí,
Ọtí lójú ogun Ojú-ìwé 26. àtúnṣe
Ifá kan wáa jẹ dé,
Odù kan wáá gàtẹ:
Ẹ bi mí:
Ẹ ní “Fáa kí ni?”
Ifá “Ọtí nílé ayé”
Tibi Tire Ojú-ìwé 27-28. àtúnṣe
Àìlera ni bàbá ìlera,
Àìsàn sì lokùnfà ìwòsàn.
Ẹní paraa rẹ̀ ní líle ṣánṣán,
Ó lè jọ́gàá aláìlera.
Ẹní lóun ò nílòò ìwòsàn
Ó le máa fakùn àìsàn mọ́dò
Ìpàdé Ọ̀rẹ́ Mẹ́rin Ojú-ìwé 29. àtúnṣe
Lágbájá ń wá owó kágbó,
Tẹ̀mẹ̀dù sì ń wá ọlà kájù
Gbogbo wọn ń sá kíjokíjo.
Lágbájá pàdé Owó-tàbíyì,
Tẹ̀mẹ̀dù pàdé Ọlà-tàbí-ẹ̀yẹ;
Ọwọ́ Àìrí Ojú-ìwé 30. àtúnṣe
Kò sẹ́ni tó mọ lé ayé tán,
Kò sẹ́ni ó mọ bi à ń rè gan-an.
Ṣùgbọ́n ṣáá, ọwọ́ kan ń bẹ tó ń ṣiṣẹ́,
Iṣẹ́ tó ń ṣe ò lóùnkà;
Ọwọ́ àìrí mà lọwọ́ yẹn o.
Nínú-un ká ṣiṣẹ́ láyé,
Orí tó sunwọ̀n Ojú-ìwé 30-31. àtúnṣe
Orí tí ò sunwọ̀n a bà lú jẹ́,
Orík tó bá sunwọ̀n a tún un ṣe.
Orí tí ò sunwọ̀n ní í tú lùú,
Orí tó pé a bá ní kó o jọ.
ẹní rórí tó sunwọ̀n tí kò yìn ín,
Ẹ jẹ́ ó re lé Olórí-wíwú-tutu.
Òdìkejì Àròkàn Ojú-ìwé 32. àtúnṣe
“Àròkàn, Àròkàn, Àròkàn,
“Àwọn ló ń bÁsúu-ùndákẹ́ sáyé.
“Àwọn ni baba ńláa rẹ,
“Àwọn ni babaláwo tó mọ̀ ọ́n kì.
“Ìyá ńláa rẹ̀ ló ń jÁròójù,
“Òun gan-an lAmúlẹ́nubíabẹ”
Ó kárí Ayé Ojú-ìwé 33-34. àtúnṣe
Ẹni ó lówó tí ò ní Àmúmọ́ra
Ẹni tí ò lówó tó mà ní Àmúṣayé,
Olúkálukú a mọ hunt i ń bá un fínra.
Kò wọ́n òpìjẹ̀;
Kò wọ́n Ayáwo,
Kò sì wọ́n Awínni.
Ìdúró ò sí Ojú-ìwé 35. àtúnṣe
“Ìdúró ò sí, ìbẹ̀rẹ̀ ò sí,
Ọmọ ayé kúkú ti gbódó mì.”
Un ni Lákáṣegbé wí tó fi ṣojú yáwú,
Ó ṣojú yáwú, ó bá gbéra sọ.
Ó lóun ò níí rojú mọ́ láéláé,
Ó lérè ojú-ríro-kókó ò sí ní bì kankan.
Àdúrà fún Ìrìn Gbẹ̀rẹ̀ Ojú-ìwé 35-36. àtúnṣe
“Arìnrìngbẹ̀rẹ̀ ni yóò móyè délé,
Asíretete ò kúkú ní í róyè kankan jẹ.”
Ìrókò ga gíga ńlá,
Ó ga jAgbọ́teku-rò-fẹ́yẹ.
Àyànmọ́ wọn ò tó wà.
Ṣe un wọ́n bá ṣe ni jíjẹ.
Àyànmọ́ ò tó ìwà Ojú-ìwé 37. àtúnṣe
Bó o lórí lọ́wọ́,
Bó ò níwà pẹ̀lú ẹ̀;
Apẹ lórí tó o ń gbé kiri.
Ìwà níí mú ni í là,
Ìwà níí sọ ni í datọrọjẹ.
Ọ̀rọ̀ Ìdárayá Ojú-ìwé 38-39. àtúnṣe
Àpárá dùn lẹ́gbẹ́,
Àwàdà wuyì lọ́gbà.
Eré sunwọ̀n láwùjọ ẹgbẹ́ ẹni.
Wọ́n ní “Bá a bá rọ́lọ́rọ̀ ẹni tán,
Sọ̀rọ̀sọ̀rọ̀ là á dà kalẹ”.
Ìgbàgbé Olóòṣà Ojú-ìwé 40-41. àtúnṣe
Wọ́n ní “Bí kúu lé ò pa ni,
“Tòde ò rí ni gbé mì.”
Un ló mú mi rántí Olóòṣà kan Òòṣà kàn,
Tó ń ṣè gbàgbé pọ̀ mọ́ gbàgbọ́.
Tó ń fouńjẹ ajá féhoro jẹ.
Ìyàwó Olóòṣà sì rèé;
Ojú ti rà Ojú-ìwé 42. àtúnṣe
Kàkà kó ní “Ojú ti là”,
“Ojú ti rà” ló wá sẹ́ẹ̀kẹ́ẹ̀ Gbìrà.
Àṣìṣee rẹ̀ sì wáá wúlò gidi!
Nígbà ojú ṣì wà lórúnkún,
Nígbà ojú ṣì wà lórúnkún,
Nígbà ojú ṣẹ̀ṣẹ̀ gbó tí kò tíì rà,
Aájò Ara Ojú-ìwé 43-44. àtúnṣe
Aájò ara bẹ̀rẹ̀ lórí ìmọ́tótó,
Ìmọ́totó tó borí àrùn mọ́lẹ̀;
Bọ́yẹ́ ti í borí ooru.
Aájò ara dórí oúnjẹ àtàtà,
Oúnjẹ àtàtà ti í ṣare lóore.
Oúnjẹ tíí mú orí pé,
Ayé yí Ojú-ìwé 45. àtúnṣe
Òbìrí, ayé yi dà sí tàtijọ́,
Òbìrì, ayé yí dà sí tìgbà kan. Ọmọ ò sin baba bíi tìjọ́sí mọ́,
Baba ló wá ń sin ọmọ bíí rẹ́rẹ.
Ọmọbìnrin ò sìn yá rẹ̀ mọ́.
Ìyá ọmọ ló wá ń sin ọmọ dé bi tó ga.
Owó ti kúrò ní Àpèṣẹnukótó,
Ojúlarí Ojú-ìwé 46-47. àtúnṣe
Bábá kan bàbà kàn,
Ó wà lẹ̀gàn níjọ́sí,
Ó lórí lọ́wọ́, ó láya tó dáa.
Aya ọ̀hún sunwọ̀n, ó yẹ̀nìyàn.
Ṣùgbọ̀n ó pẹ́ korí tóó dá a.
Ó tojú sú gbobgo àdúgbò.
Ìlú Ọ̀dájú Ojú-ìwé 48. àtúnṣe
Ẹ̀kọ́, ìlú ọ̀dájú.
Èkó, ìlú ìmọtara.
Yorùbá bọ̀ wọ́n ní ‘Òjú níí rójú ṣàánú’
Èkó ní ‘Alátiṣe níí màtiṣe’
Yorùbá ní ‘ Ká fọ̀tún wẹ̀sì,
Ká fòsì wẹ̀tún;
Ẹ̀dá náà ń dá nǹkan Ojú-ìwé 49. àtúnṣe
Kí lènìyàn wà láyé fún?
TẸ́lẹ́dàá, fi ṣẹ̀dá ènìyàn?
TẸ́lẹ́dàá, ṣẹ̀dá ènìyàn?
Tó sì fún wọn lágbára?
Ó ní ki wọn ó má dá hun ti wọ́n fẹ́,
Yàtọ̀ sénìyàn tó já raa wọn,
Aláìníkan-án-ṣe Ojú-ìwé 50-51. àtúnṣe
Ifá ní Ṣòtítọ́ọ́ọ́,
Má mà ṣè kà ènìyàn o o.
Ṣòtítọ́ o o ò,
Má mà ṣè kà ènìyàn o o.
Ẹní bá ṣòtítọ́ọ́ọ́
Ni ó tẹlẹ̀ yí pẹ́ o o.’
Ọ̀gá ńlá Ojú-ìwé 52-53. àtúnṣe
Ẹyẹ kan,
Ẹ̀yẹ̀ kàn,
A máa jẹ́ Ọ̀gá-ńlá.
Inúu pápá ló ń gbé kiri.
Ìdí tó fi ń jẹ́ Ọ̀gá-ńlá-wòr`o ní kíkún,
Kò sẹ́ni tó le fìdí ẹ̀ hanni?
Ẹ̀bẹ̀ Ojú-ìwé 54. àtúnṣe
Òkun layé o, ọ̀rẹ́ẹ̀ mi.
Òkun layé o; ènìyàn ibẹ̀, un lọ̀sà.
Odò tún layé pẹ̀lú;
Bí olórúkọọ́ jórúkọ.
Orí, wáá dá wa pé, jọ̀wọ́:
Káyé má mu wá lómi.
Afẹ́fẹ́ Layé Ojú-ìwé 55. àtúnṣe
Bí ò sí afẹ́fẹ́
Ẹnì kan ò pẹ́ láyé.
Bí ò sì sí òòrùn
Ilè kàn ò gbẹ bòrọ̀bọ̀rọ̀.
Afẹ́fẹ́ tó fẹ́.
Tá a rí fùrọ̀ adìyẹ;
Ẹbọ Adárúdurùdu Ojú-ìwé 56. àtúnṣe
Ọ̀rọ̀ dọ̀rọ̀ àwa araa wa –
Gbogbo àgbààgbà tó wà nílẹ̀ yí
Ẹ dákun, ẹ bá mi gbérò yìí yẹ̀ wò.
Èrò ọ̀hùn ò déédéé tu yọ látàríi kékeré Ọ̀jẹ̀-
Kékeré Ọ̀jẹ̀ tí ń kẹ́ṣà-pípè.
Àgbà Ọ̀jẹ̀ ló ti kéwì ṣáájú,
Ojú ò tórí Ojú-ìwé 57. àtúnṣe
Ojú ẹ̀dá ò tórí –
Ó ṣe,
Ó pọ̀;
Ó mà ṣe o!
Ṣé bẹ́dàá bá dẹjú rẹ̀
Yóò rímú.
Àkàntì Ojú-ìwé 58. àtúnṣe
Àkàntì tí ẹ rí yìí
Ogun tó nípọn ni.
Mo fẹ́rẹ́ pa á
Ǹjó ṣeé sè mọ́bẹ̀?
Ó fẹ́rẹ̀ẹ́ gbó
Njó ṣeé ká jẹ?
Ká Ṣọ́ra Ojú-ìwé 59. àtúnṣe
Igba ẹká níí fọwọ́ọ́ tilé;
Igba aláàmù níí fọwọọ́ tògiri;
Un nilé fi í fúró sán-ún.
Ùn lògiri fi í ní bàlẹ̀-ọkàn.
Omi ní ń bẹ lẹ́yìn ẹja
Un lẹja fi joyè abìwẹ̀gbàdà.
Òwèrè Ènìyàn méjì péré Ojú-ìwé 60-61. àtúnṣe
Alàgbà kan ń bẹ nífẹ̀ Oòyè
Amọ́bíọjọ́ ní í jẹ́;
Ó mọ́ níkùn tán, ó tún mọ́ lóde ara.
Òun ló kọ́ wa lọ́rọ̀ kan, àjímáarán;
Ó kọ́ wa lọ́rọ̀ kan, àjígbéyẹ̀wò -.
Ó lénìyàn méjì péré
Ìgbaradì: Ẹbọ Àyípadà Ojú-ìwé 62. àtúnṣe
Omí parade
Omí dọtí.
Àgbàdó paradà
Ó dògì.
Èbù ìjọ̀sí paradà
Àdúrà fún wọn Ojú-ìwé 1 àtúnṣe
Wọ́n ní “Ta ló wà nínú ọgbà náà?
Bí mo ti tajú kán-án,
Ni mo bá rọ́mọ kékeré kan.
Ó ní “Ẹ̀yin babaláwo ayé, ẹ mà kúù dúró,
“Ẹ̀ kúù dúró tÌbádùnmọ́pẹ́,
“Ẹ kú àìgbò lẹ́yìn ọmọ je-n-jele.
“Bó bá jẹ́ mo dáyé wá ṣé ǹ bá ti tán,
“Bó sì jẹ́ mo nìkan rìn, mà ti rìn jùnù.
Mo kíi yín fún iṣẹ́ẹ yín,
Ìwúlò Ewì Ojú-ìwé 2. àtúnṣe
Béwì kéré tá `o rí rú ẹ̀ rí,
Ká má fojúdewì ló tọ̀nà,
Ká kúkú rò ó wò ló tọ́,
Ká tú ọgbọ́n tó fi pamọ́ yọ.
Torí béwì kéré bá ò rí rú ẹ̀ rí,
Aboyún ọ̀rọ̀ ní ń bẹ ní kùn-un rẹ̀.
Ewì le wèrò òmùgọ̀ tí à ń rò lọ́wọ́,
Kó bá ni sọ ọ́ dọgbọ́n tó jinná gidi.
Èrò Ọkàn Ojú-ìwé 3 àtúnṣe
Mélòómélòó òjò ló ti rọ̀ látàrí;
Tó rọ̀ níbẹ̀, tílẹ̀ sì ti fi mu?
Mélòómélòó lèrò tó ti sọ sí ni lọ́kàn;
Tó sọ sí ni lọ́kàn ṣùgbọ́n tí ò dúró rárá?
Mélòómélòó lèrò tó ti sọ lódòo kùn,
Tó sọ níbẹ̀, tó sì tún mòòkùn lọ bí ẹja?
Ìwọ̀n ẹja tá a bá fiwò gbé ńkọ́,
Ṣéun náà la lè jẹ.
Ìwọ̀n ẹja tá a bá fàwọ̀n kó,
Ṣóun náà la lè tà.
Má ṣe bẹ́ẹ̀ Ojú-ìwé 4-5. àtúnṣe
Wọ́n ní “Ṣe bó o ti mọ,
“Ṣenu ní wọ̀n-ọn tòkèlè;
“Ṣòkèlè ní wọ̀n-ọn tọ̀fun
“Dá ṣọ pé-ń-pé o mú bo ra rúgúdú,
“Rẹ̀wù òun ṣòkòtò ní wọ̀n o lè wọ̀.
“Kọ́lé apá-ọ̀bún-ká,
“Má ṣe yà ní sọ ajunilọ.
“Bágbọ̀n bá ga lágajù,
“Sá fẹ́kọ inú ẹ̀ wéréwéré.
“Nítorí pẹ́ni ó ju ni lọ tefétefé
Láaróyè Ojú-ìwé 6. àtúnṣe
Ọlọ́run tó layé lọ̀run.
Ló fÈṣù sílé ayé;
Pé kó máa báráyé fínra.
Ẹ̀sù kò ní bìkan àgbámú,
Ibikíbi ló le fi gúnni.
Eji lÈṣù, kò bẹ́nìkan ṣọ̀rẹ́,
Ẹni Akọ́gọ fẹ́ ní í pa nígi.
Láaróyè kò bẹ́nìkan ṣọ̀tá,
Ọrọ̀ gidi Ojú-ìwé 7. àtúnṣe
Bó o lówó bó ò lọ́rọ̀ láyé,
Ṣe bówó báńsá lo kó jọ.
Ìgbà tó o kówó ka lẹ̀ẹ́-lẹ̀,
Bónílé wọlé dé ńkọ́?
Ti taa ni kóhun tó o ní ó jẹ́ gidi?
Bó o tún fowó ṣe hun iyì sílẹ̀,
Bónílé bà dé ńkọ́?
Ṣùgbọ́n bó o rí ná tó o sì rí lò láyé,
Tálàáfíà sùn ẹ́ bọ̀,
Ìlú Ìgàngàn Ojú-ìwé 8-10. àtúnṣe
Ọmọ kékee ilé, ẹ sáré wá.
Àgbà tí ń bọ̀ lọ́nà, ẹ tẹsẹ̀ mọ́rìn
Ẹ yé, ẹ wá ná, ẹ wáà gbọ́rọ̀ ẹnu àwa.
Àwaa kékeré ìwòyí tó mú létè bí ìṣó;
Àwaa kékeré ìwòyì tó buyọ̀ setè.
Kí lohun tá a fẹ́ẹ́ wí fáyé?
À ní kí lohun tá a fẹ́ẹ́ sọ sóde?
Ìtàn ló sọ fún wa nílẹ̀ yi.
Ìlú Làǹlátẹ̀ Ojú-ìwé 11. àtúnṣe
Bá a bá fa gbùrù,
Gbùrù á mà fa nǹkan.
Bá a bá gbọ́ Làǹlátẹ̀ sétí,
Ó le dún létí bí “Ìlú Ọ̀tẹ̀”.
Làǹlá ò mà mà lọ́tẹ̀ ńnú rárá,
Làǹlá ló tẹ bi wọ́n ń gbé ni.
Làǹlá ò fẹ́gàn rárá,
Ṣe ni wọ́n ń bá raa wọn wá re.
Ìlú Èrúwà Ojú-ìwé 12. àtúnṣe
Bá a bá kọ́ gbọ́ “Èrúwà”,
Ó jọ “Bí-èrú-wà” létí
Ṣùgbọ́n ní gàsíkíyá, èrú-ṣíṣe kọ́ nì pìlẹ̀ ìlú,
Èrú-ṣíṣe kò ráyè níbẹ̀;
À ní, èrú-ṣíṣe ò sí lọ́rọ̀ọ tiwọn.
Èrú iṣu ló pọ̀ níbẹ̀ rí,
Tí wọn ń tà férò ọ̀nà.
Wọ́n wá ń polówó iṣu tó tú dáadáa.