Aláàfin Abípa, òun ni a tún mọ̀ sí l Ògbólú tàbí Ọba Moró,[1] jẹ́ Àlááfín Ọ̀yọ́ àti àgbègbè rẹ̀. Wọ́n gbà pé ó wà ní ìtẹ́ ọba Àlááfín ní nǹkan bí sẹ́ńtúrì 16 àti 17. [2]

King Abipa/Ogbolu or Oba M'oro
Orúkọ mírànOba M'oro
Iṣẹ́Alaafin of the Oyo empire

Nígbà èwe

àtúnṣe

Àlááfín Abípa jẹ́ ọmọ bíbí was the son of Egunoju àti ọkàn nínú àwọn olorì rẹ̀. Wọ́n ní wón bí i lọ́nà lọ́jọ́ tí wọ́n ń ṣayẹyẹ kan lọ́nà àtisúnmọ́ ìlú Igboho (wọ́n fún lórúkọ láti inú ọ̀rọ̀ yìí a bí i sí ipà - 'ẹni tí wọ́n bí sí ipà ọ̀nà tàbí ẹ̀bá ọ̀nà').[2]

Kí ó tó di àkókò rẹ̀ ọba mẹ́ta tí jẹ́ lórí Ọ̀yọ́ sí Ìgbòho dípò Ọ̀yọ́ ilé nítorí ìbẹ̀rù àwọn Nupe àti àwọn mìíràn. Abípà ni Àlàáfíà Ọ̀yọ́ tí ó dá olú-ìlú Ọ̀yọ́ padà sí Ọ̀yọ́-ilé lẹ́yìn tí wọ́n ti borí àwọn ogún ti ó ń jàwọ́n láti ìta. Pípadà sí Ọ̀yọ́-ilé wáyé ní sẹ́ńtúrì kẹtàdínlógún (17 Century).[3]

Gẹ́gẹ́ bí àṣà, àwọn ènìyàn pàtàkì kan tí wọ́n fẹ́ kí olú-ìlú Ọ̀yọ́ ṣì dúró sí Ọ̀yọ́-Ìgbòho rán àwọn olórò òfegè láti lọ ṣe aṣojú ọfegè nígbà tí àwọn ènìyàn Abípà ṣe àbẹ̀wò sí olú-ìlú àtijọ́.[4] Abípà mọ nípa èyí, ló bá rán àwọn ọdẹ lọ láti mú àwọn olórò òfegè wọ̀nyí. Nítorí èyí ni wón ṣe ń pè é ní Ọba mórò, Ọba tí ó mú orò. Ìtàn yìí ṣì ń jẹyọ lásìkò ọdún ni Ọ̀yọ́ àti nígbà tí wọ́n bá fẹ́ fi ọba Àlááfín tuntun jẹ.[4]

Nígbà tí ọdún òye wọ Ọ̀yọ́-ilé, Abípà fi ọmọkùnrin aṣẹ̀ṣẹ̀bí rúbọ. Ìdí nìyí tí wón fi máa ń kì í ní "Ọba amórò tó f'ọmọ rẹ̀ rúbọ fún àlàáfíà ayé'.[4]

Obalokun ló j'ọba lẹ́yìn rẹ̀.Àdàkọ:Cn

Àwọn Ìtọ́kasí

àtúnṣe
  1. Law, Robin (1984). "How Truly Traditional Is Our Traditional History? The Case of Samuel Johnson and the Recording of Yoruba Oral Tradition". History in Africa 11: 195–221. doi:10.2307/3171634. ISSN 0361-5413. JSTOR 3171634. 
  2. 2.0 2.1 Smith, Robert (1965). "The Alafin in Exile: A Study of the Igboho Period in Oyo History". The Journal of African History 6 (1): 57–77. doi:10.1017/s0021853700005338. ISSN 0021-8537. 
  3. African sacred spaces : culture, history, and change. ISBN 9781498567428. OCLC 1077789018. 
  4. 4.0 4.1 4.2 Smith, Robert (1988). Kingdoms of the Yoruba. Currey. ISBN 0852550286. OCLC 813599097.