Olóyè Alaba Lawson (tí a bí ní Omidan Alaba Oluwaseun Lawson ni ọjọ kejì-dín-lógún oṣú kínní ọdún 1951) jẹ ọmọ orilẹ-èdè Naijiria; olokoowo nla, oniṣowo agba ati ọmọwe sì ni pẹlu. Òun ni ó jẹ́ obinrin àkọ́kọ́ tí ó jẹ aarẹ ẹgbẹ NACCIMA ati Alága Ìgbìmọ̀ awọn Alakoso ti ile ẹko gbogboniṣe, Moshood Abiola ni Ìpínlẹ̀ Ogun ni orilẹ-ede Naijiria.

Alaba Lawson
Ọjọ́ìbíOṣù Kínní 18, 1951 (1951-01-18) (ọmọ ọdún 73)
Abeokuta, Ogun State, Nigeria
Orílẹ̀-èdèNigerian
Orúkọ mírànIyalode Alaba Lawson
Iléẹ̀kọ́ gíga
  • Abeokuta Girls Grammar School
  • St. Nicholas Montessori Teachers’ Training College
Iṣẹ́
Ìgbà iṣẹ́1977–present
EmployerNACCIMA
Board member ofChairman, Board of Governing Council, Moshood Abiola Polytechnic, Ogun State
Websitealabalawson.org

Olóyè Lawson ti di ipo aarẹ agbarijọpọ awọn lọbalọba to jẹ́ obinrin ni orilẹ-ede Naijiria (Forum of Female Traditional Rulers in Nigeria).

Ìbẹ̀rẹ̀ igbe ayé àti ètò ẹkọ àtúnṣe

A bi Alaba si inu ẹbi Jibolu-Taiwo ti ìlú Abeokuta, ti i ṣe olu ilu fun ipinlẹ Ogun, níbi ti o ti pari ile-ẹkọ alakọbẹrẹ ati girama ni ile-ẹkọ St. James’ African Primary School, Idi-Ape, Abeokuta laarin ọdun 1957 ati 1962 fun ẹkọ alakọbẹrẹ ati Ile-ẹkọ girama fun awọn obinrin (Abeokuta Girls Grammar School), Abeokuta, eleyi ti o pari ni ọdun 1968[1] ki o to tẹsiwaju lati lọ si ile ẹkọ fun awọn olukọni ni St. Nicholas Montessori Teachers’ Training College ti o wa ni Prince's Gate, England ni ọdun 1973 ni bi ti o ti peregede ti o si gba iwe ẹri diploma ninu ikọni (Diploma in Education)[2].

Awọn Itọkasi àtúnṣe

  1. https://www.vanguardngr.com/2017/05/naccima-gets-first-female-national-president/
  2. "Ẹda pamosi". Archived from the original on 2020-02-19. Retrieved 2022-05-20.