Bí Ìpínlẹ̀ Èkó ṣe ń dojú ìjà kọ COVID-19

Ní ọjọ́ kẹtàdínlọ́gbọ̀n oṣù kejì ọdún 2020 ni àjàkálẹ̀ àrùn COVID-19 fìdí sọlẹ̀ sí orílẹ̀-èdè Nàìjíríà. Èyí wáyé látipasẹ̀ arákùnrin Italy kan tí ó padà sí Nàìjíríà pẹ̀lú ọkọ̀ òfurufú ní ọjọ́ kẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n oṣù kejì ọdún 2020.

Bí Àrùn náà ṣe tànkálẹ̀ ní Ìpínlẹ̀ Èkó àtúnṣe

Ní ọjọ́ kẹtàdínlógún oṣù kẹta, Ìpínlẹ̀ Èkó fìdí ìṣẹ̀lẹ̀ kejì múlẹ̀ látara ọdọ́mọbìnrin kan tí ń ṣe ọmọ ọgbọ̀n ọdún tí ó jẹ́ ọmọ ilẹ̀ Nàìjíríà tó ṣẹ̀ṣẹ̀ padà dé láti ilẹ̀ aláwọ̀funfun ní ọjọ́ kẹtàlá oṣù kẹta.[1]

Ní ọjọ́ kejìdínlógún oṣù kẹta, ìpínlè Èkó tún ṣàwárí ìṣẹ̀lẹ̀ tuntun mẹ́rin. [2]

Ní́ ọjọ́ kọkàndínlógún oṣù kẹta, a tún rí ìṣẹ̀lẹ̀ tuntun mẹ́rin lórí àrùn COVID-19 ní Ìpínlẹ̀ Èkó. [3] [4] Lọ́jọ́ kan náà ni a gbọ́ pé arákùnrin tó mú àjàkálẹ̀ àrùn náà wọ orílẹ̀-èdè Nàìjíríà ti gba òmìnira lọ́wọ́ àjàkálẹ̀ àrùn náà. Èyí sì já sí àṣeyọrí àkọ́kọ́ tí ìpínlẹ̀ Èkó ní lórí àrùn náà.[5][6]

Ní ọjọ́ kọkànlélógún oṣù kẹta, ìpínlẹ̀ Èkó tún ṣàwárí ìṣẹ̀lẹ̀ méje mìíràn.[7]

Ní ọjọ́ kejìlélógún oṣù kẹta, ìṣẹ̀lẹ̀ mẹ́fà mìíràn ni ìpínlẹ̀ Èkó tún ṣàwárí.[8][9]

Ní ọjọ́ kẹtàlélógún oṣù kẹta, ìpínlẹ̀ Èkó tún ṣàwárí ìṣẹ̀lẹ̀ mẹ́fà.[10] wọ́n sì tún fìdí ẹni àkọ́kọ́ tí ó jẹ́ aláìsí látipasẹ̀ àrùn COVID-19 múlẹ̀, ẹni tí ó jẹ́ àgbàlagbà ọmọ ọdún mẹ́tàdínláàádọ́rin tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Suleiman Achimugu, onímọ̀ ẹ̀rọ àti ọ̀gá àgbà tẹ́lẹ̀ fún ilé iṣẹ́ Pipeline and Product Marketing, ẹnití ó ṣẹ̀ṣẹ̀ dé láti ìlú aláwọ̀funfun pẹ̀lú àìlera ara.[11]

Ní ọjọ́ kẹrìnlélógún oṣù kẹta, ìpínlẹ̀ Èkó ṣàwárí ìṣẹ̀lẹ̀ kan.[12]

Ní ọjọ́ kẹẹ̀dọ́gbọ̀n oṣù kẹta, ìpínlẹ̀ Èkó ṣàwárí ìṣẹ̀lẹ̀ mẹta mìíràn.[13]

Ní ọjọ́ kẹrìndínlọ́gbọ̀n oṣù kẹta, ìpínlẹ̀ Èkó ṣàwárí ìṣẹ̀lẹ̀ méjìlá tuntun. [14].

Ní ọjọ́ kẹtàdínlọ́gbọ̀n oṣù kẹta, ìpínlẹ̀ Èkó rí ìṣẹ̀lẹ̀ mẹ́jọ mìíràn.[15] Lọ́jọ́ kan náà ni gómìnà Ìpínlẹ̀ Èkó, Babajide Sanwo-Olu ṣe ìkéde lórí àwọn ìjọba ìbílẹ̀ Èkó tí ó ní iye ìṣẹ̀lẹ̀ tí ó pọ̀ jù lọ. Àwọn ìbílẹ̀ náà ni: Etí Ọ̀sà àti Ikeja.[16]

Ní ọjọ́ kejìdínlọ́gbọ̀n oṣù kẹta, ìpínlẹ̀ Èkó rí ìṣẹ̀lẹ̀ méje mìíràn.[17]

Ńi ọjọ́ kọkàndínlọ́gbọ̀n oṣù kẹta, ìpínlẹ̀ Èkó rí ìṣẹ̀lẹ̀ mẹ́sàn-án tuntun.[18]

Ní ọgbọ̀n ọjọ́ oṣú kẹta, ìpínlẹ̀ Èkó tún rí ìṣẹ̀lẹ̀ mẹ́tàlá mìíràn.[19]

Ní ọjọ́ kìíní oṣù kẹrin, ìpínlẹ̀ Èkó rí ìṣẹ̀lẹ̀ mẹ́sàn-án mìíràn.[20][21]

Ní ọjọ́ kejì oṣù kẹrin, ìpínlẹ̀ Èkó rí ìṣẹ̀lẹ̀ méje mìíràn.[22] Lọ́jọ́ kan náà ni wọ́n ṣe ìkéde pé èèyàn mọ́kànlá lára àwọn tí ó kó àrùn náà ní ó ti bọ́ tí ó sì ti ní ìwòsàn pípé.[23]

Ní ọjọ́ kẹta oṣù kẹrin, ìpínlẹ̀ Èkó rí ìṣẹ̀lẹ̀ mọ́kànlá mìíràn.[24]

Ní ọjọ́ karùn-ún oṣù kẹrin, ìpínlẹ̀ Èkó rí ìṣẹ̀lẹ̀ mọ́kànlá mìíràn.[25][26]

Ní ọjọ́ keje oṣù kẹrin, ìpínlẹ̀ Èkó rí ìṣẹ̀lẹ̀ mẹ́wàá mìíràn.[27]

Ní ọjọ́ kẹjọ oṣù kẹrin, ìpínlẹ̀ Èkó rí ìṣẹ̀lẹ̀ mẹ́ẹ̀ẹ́dógún mìíràn.[28]

Ní ọjọ́ kẹsàn-án oṣù kẹrin, ìpínlẹ̀ Èkó rí ìṣẹ̀lẹ̀ mẹ́tàlá mìíràn.[29]

Ní ọjọ́ kẹwa oṣù kẹrin, ìpínlẹ̀ Èkó rí ìṣẹ̀lẹ̀ mẹ́jọ mìíràn.

Ní ọjọ́ kọkànlá oṣù kẹrin, ìpínlẹ̀ Èkó rí ìṣẹ̀lẹ̀ mọ́kànlá mìíràn.[30]

Ní ọjọ́ kejìlá oṣù kẹrin, ìpínlẹ̀ Èkó rí ìṣẹ̀lẹ̀ méjì mìíràn.[31]

Ní ọjọ́ kẹtàlá oṣù kerin, ìpínlẹ̀ Èkó rí ìṣẹ̀lẹ̀ mẹ́tàlá mìíràn.[32]

Ní ọjọ́ kẹrìnlá oṣù kẹrin, ìpínlẹ̀ Èkó rí ìṣẹ̀lẹ̀ mẹ́ẹ̀dọ́gbọ̀n mìíràn.[33] [34]Ìpínlẹ̀ Èkó kéde pé àwọn òṣìṣẹ́ wọn ti ṣe àbẹ̀wò sí àwọn ojúlé tí ó tó 118,000 láàrin ọj́ọ́ méjì tí wọ́n sì rí iye àwọn ènìyàn tí ó tó 119 tí wọ́n ní àmì tí ó máa ń yọ lára àwọn tí ó ní àjàkálẹ̀ àrùn náà lára.[35]

Ní ọjọ́ kẹẹ̀dógún oṣù kerin, ìpínlẹ̀ Èkó rí ìṣẹ̀lẹ̀ méjìdínlógún mìíràn. [36]

Ní ọjọ́ kẹrìndínlógún oṣù kẹrin, ìṣẹ̀lẹ̀ mọ́kàndínlógún ní a rí ní Ìpínlẹ̀ Èkó.[37]

Ní ọjọ́ kẹtàdínlógún oṣù kẹrin, ìṣẹ̀lẹ̀ méjìlélọ́gbọ̀n mìíràn ni a rí ní Ìpínlẹ̀ Èkó.[38]

Ní ọjọ́ kejìdínlógún oṣù kẹrin, ìṣẹ̀lẹ̀ mẹ́tàlélógún mìíràn ni a rí ní Ìpínlẹ̀ Èkó.[39]

Ní ọjọ́ kọkàndínlógún oṣù Kẹrin, àádọ́rin ìṣẹ̀lẹ̀ tuntun lórí àrùn Covid-19 ni a rí ní Ìpínlẹ̀ Èkó.[40]

Ní ọjọ́ kọkànlélógún oṣù kẹrin, ìpínlẹ̀ Èkó ṣàwárí ìṣẹ̀lẹ̀ mọ́kàndínlógójì mìíràn.[41]

Ní ọjọ́ kejìlélógún oṣù kẹrin, ìṣẹ̀lẹ̀ mẹ́rìnléláàádọ́rin ni a rí ní ìpínlẹ̀ Èkó.[42]

Ní ọjọ́ kẹtàlélógún oṣú kẹrin, ìpínlẹ̀ Èkó ṣàwárí ìṣẹ̀lẹ̀ méjìdínlọ́gọ́rin mìíràn.[43]

Ni ojo kerinlelogun osu kerin, ọgọ́rin ìṣẹ̀lẹ̀ ni a rí ní Ipinle Èkó.[44]


Ní ọjọ́ kẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n oṣù kẹrin, èjìdínlọ́tà-léní-ẹgbẹ̀fà èèyàn ni ó ní àrùn covid-19 ní ìpínlẹ̀ Èkó.

Ìhà tí Ìpínlẹ̀ Èkó kọ sí Àrùn náà àtúnṣe

Ní ọjọ́ kọkànlélọ́gbọ̀n oṣù kẹta ọdún 2020, ìpínlẹ̀ Èkó bẹ̀rẹ̀ ìsémọ́lé ní pẹrẹu.[45] Gómìnà ìpínlẹ̀ Èkó rọ àwọn èèyàn ní ìpínlẹ̀ náà láti dúró sílé, ó sì rọ àwọn ilé-iṣẹ́ lọ́lọ́kan-ò-jọ̀kan láti dáwọ́ iṣẹ́ dúró àmọ́ tí àwọn òṣìṣẹ́ bá le ṣiṣẹ́ láti ilé, wọ́n le tẹ̀ síwájú.[46] Ó tún rọ àwọn ilé-ìwé aládàáni àti ìjọba kí wọ́n dáwọ́ iṣẹ́ dúró. Kódà gbogbo ènìyàn ní gómìnà ìpínlẹ̀ náà rọ̀ láti dúró sílé. Èyí ò sì yọ ilé-ìjọsìn ti Mùsùlùmí àti Kìtẹ́ẹ́nì sẹ́yìn. Àṣẹ sì wà pé kò gbọdọ̀ sí ìpéjọ pò tó ju ogún èèyàn lọ. Yálà ní ilé-ìjọsìn, ayẹyẹ, ilé-iṣẹ́ àdáni tàbí ìpéjọ pò mìíràn lóríṣiríṣi. Àṣẹ sì wà pé ẹnikẹ́ni tí owó bá tẹ̀, á fojú ba ìjìyà tó tọ́. Ìjọba náà fi lélẹ̀ pé kò gbọdọ̀ sí ìjáde tàbí ìwọlé pẹ̀lú ọkọ̀ òfurufú ní ìpínlẹ̀ náà. Àwọn ọjà káàkiri ìpínlẹ̀ náà ni ó sì ní ọjọ́ tí wọ́n ń ṣí fún títa àti rírà. Àmọ́ àwọn ọlọ́jà tó ń ta nǹkan jíjẹ ni ààyè wà fún láti ṣí ṣọ́ọ̀bù wọn.

Àwọn Ìtọ́kasí àtúnṣe

  1. "Third coronavirus case confirmed in Nigeria". TheCable. 2020-03-17. Retrieved 2020-04-06. 
  2. Toromade, Samson (2020-03-18). "Nigeria confirms 5 new cases of coronavirus". Pulse Nigeria. Retrieved 2020-04-06. 
  3. Obinna, Chioma (2020-03-19). "LASG Confirms 4 more new cases of COVID-19". Vanguard News. Retrieved 2020-04-06. 
  4. "Nigeria's coronavirus cases rises to 12 with four new confirmations". The Guardian Nigeria News - Nigeria and World News. 2020-03-19. Retrieved 2020-04-06. 
  5. Published (2015-12-15). "Italian who brought coronavirus to Nigeria now negative – Lagos". Punch Newspapers. Retrieved 2020-04-06. 
  6. "UPDATED: Lagos discharges Italian who brought coronavirus to Nigeria". Punch Newspapers. 2015-12-15. Retrieved 2020-04-06. 
  7. "Nigeria records 10 new positive cases of COVID-19". Latest Nigeria News, Nigerian Newspapers, Politics (in Èdè Latini). 2020-03-21. Retrieved 2020-04-06. 
  8. "Coronavirus: Nigeria now has 26 Confirmed cases - NCDC". Latest Nigeria News, Nigerian Newspapers, Politics (in Èdè Latini). 2020-03-22. Retrieved 2020-04-06. 
  9. "BREAKING: COVID-19: NCDC confirms one new case in FCT". Latest Nigeria News, Nigerian Newspapers, Politics (in Èdè Latini). 2020-03-22. Retrieved 2020-04-06. 
  10. "Nigeria's coronavirus cases now 40 on Monday night". The Guardian Nigeria News - Nigeria and World News. 2020-03-23. Retrieved 2020-04-07. 
  11. "Achimugu, ex-PPMC boss identified as Nigeria's first coronavirus death". P.M. News. 2020-03-23. Retrieved 2020-04-07. 
  12. "Nigeria coronavirus cases rise to 44". Punch Newspapers. 2015-12-15. Retrieved 2020-04-07. 
  13. Published (2015-12-15). "Coronavirus cases hit 51 in Nigeria". Punch Newspapers. Retrieved 2020-04-07. 
  14. "14 New Cases Of COVID-19 Confirmed In Nigeria". Channels Television. 2020-03-26. Retrieved 2020-04-07. 
  15. Published (2015-12-15). "Nigeria’s coronavirus cases hit 81 as NCDC announces 11 new cases". Punch Newspapers. Retrieved 2020-04-07. 
  16. Published (2015-12-15). "Ikeja, Eti-Osa top coronavirus cases in Lagos". Punch Newspapers. Retrieved 2020-04-07. 
  17. "COVID-19: Nigeria’s cases hit 97  – Punch Newspapers". Punch Newspapers – The most widely read newspaper in Nigeria. 2015-12-15. Retrieved 2020-04-07. 
  18. Published (2015-12-15). "UPDATED: Nigeria reports 14 new coronavirus cases, total now 111". Punch Newspapers. Retrieved 2020-04-07. 
  19. Published (2015-12-15). "COVID-19 cases rise to 131 in Nigeria". Punch Newspapers. Retrieved 2020-04-07. 
  20. Published (2015-12-15). "Nigeria records 12 new COVID-19 cases, total now 151". Punch Newspapers. Retrieved 2020-04-07. 
  21. Published (2015-12-15). "Nigeria records 23 new cases of COVID-19, total now 174". Punch Newspapers. Retrieved 2020-04-07. 
  22. Published (2015-12-15). "Nigeria records 10 new coronavirus cases in Lagos, Abuja". Punch Newspapers. Retrieved 2020-04-07. 
  23. Published (2015-12-15). "Coronavirus: 11 patients recover, discharged in Lagos". Punch Newspapers. Retrieved 2020-04-07. 
  24. "BREAKING: Nigeria records six new cases of COVID-19". Latest Nigeria News, Nigerian Newspapers, Politics (in Èdè Latini). 2020-04-03. Retrieved 2020-04-07. 
  25. Published (2015-12-15). "UPDATED: Nigeria records 10 new cases of coronavirus, total now 224". Punch Newspapers. Retrieved 2020-04-07. 
  26. Published (2015-12-15). "UPDATED: Nigeria records eight new COVID-19 cases, total now 232". Punch Newspapers. Retrieved 2020-04-07. 
  27. "Nigeria records 16 new COVID-19 cases, total now 254". Punch Newspapers. 2015-12-15. Retrieved 2020-04-09. 
  28. Royal, David (2020-04-08). "Nigeria records 22 new cases of COVID-19, as total rises to 276". Vanguard News. Retrieved 2020-04-09. 
  29. Published (2015-12-15). "Nigeria records 14 new COVID-19 cases, total now 288". Punch Newspapers. Retrieved 2020-04-10. 
  30. Published (2015-12-15). "UPDATED: 10 dead as Nigeria’s coronavirus cases rise to 318". Punch Newspapers. Retrieved 2020-04-14. 
  31. Published (2015-12-15). "Nigeria records five new coronavirus cases, total now 323". Punch Newspapers. Retrieved 2020-04-14. 
  32. Published (2015-12-15). "UPDATED: Nigeria records 20 new COVID-19 cases, total now 343". Punch Newspapers. Retrieved 2020-04-14. 
  33. "UPDATED: Nigeria’s coronavirus cases now 362 after 19 test positive – Punch Newspapers". Punch Newspapers – The most widely read newspaper in Nigeria. 2015-12-15. Retrieved 2020-04-17. 
  34. Published (2015-12-15). "UPDATED: Nigeria records 11 new coronavirus cases in Lagos, total now 373". Punch Newspapers. Retrieved 2020-04-17. 
  35. "After Visiting 118,000 Households, We Identified 119 Persons With COVID-19 Symptoms –Lagos Government". Sahara Reporters. 2020-04-14. Retrieved 2020-04-17. 
  36. Published (2015-12-15). "UPDATED: 12 dead as Nigeria’s coronavirus cases rise to 407". Punch Newspapers. Retrieved 2020-04-17. 
  37. Published (2015-12-15). "UPDATED: Nigeria records 35 new coronavirus cases, total now 442". Punch Newspapers. Retrieved 2020-04-17. 
  38. Published (2015-12-15). "UPDATED: 17 dead as Nigeria’s coronavirus cases jump to 493". Punch Newspapers. Retrieved 2020-04-17. 
  39. Published (2015-12-15). "Nigeria records 19 deaths as coronavirus cases hit 542". Punch Newspapers. Retrieved 2020-04-20. 
  40. Published (2015-12-15). "21 dead as coronavirus spreads to 21 states, Abuja". Punch Newspapers. Retrieved 2020-04-20. 
  41. Published (2015-12-15). "UPDATED: Nigeria records 117 new coronavirus cases, total now 782". Punch Newspapers. Retrieved 2020-04-22. 
  42. Published (2015-12-15). "UPDATED: 28 dead as Nigeria’s coronavirus cases rise to 873". Punch Newspapers. Retrieved 2020-04-23. 
  43. "Nigeria records 108 new COVID-19 cases, total now 981". Punch Newspapers. 2015-12-15. Retrieved 2020-04-24. 
  44. Published (2015-12-15). "UPDATED: Nigeria’s coronavirus cases pass 1000, death toll now 32". Punch Newspapers. Retrieved 2020-04-25. 
  45. "Nigeria imposes lockdown in cities of Lagos and Abuja to curb coronavirus". France 24. 2020-03-29. Retrieved 2020-04-25. 
  46. "How Nigeria is faring nearly two weeks into COVID-19 lockdown". The Africa Report.com. 2020-04-10. Retrieved 2020-04-25.