Festus 'Adegboye' Onigbinde (ọjọ́ìbí 5 Oṣù Kẹta, 1938 ní Modakeke) ni olùkọ̀ bọ́ọ́lù-àfẹsẹ̀gbá ará Nàìjíríà. Ó ṣe olùkọ́ fún ẹgbẹ́ agbábọ́ọ́lù orílẹ̀-èdè Nàìjíríà ní ibi ìdíje Ife-ẹ̀yẹ Àgbáyé FIFA 2002,[2] kó tó di ìgbà yìí, ó tún ti jẹ́ olùkọ́ fún ẹgbẹ́ agbábọ́ọ́lù orílẹ̀-èdè Nàìjíríà làrin ọdún 1982 àti 1984. Ní 1984, Onigbinde mú Nàìjíríà dé òpin ìdíje Ife-ẹyẹ àwọn Orílẹ̀-èdè Áfríkà ọdún 1984. Náìjíríà kùnà lọ́wọ́ Kamẹrúnù pẹ̀lú góólù 1-3 nínú ayò náà. Lẹ́yìn èyí ní ọdún 1984, ó di olùkọ́ fún Shooting Stars Sports ClubIbadan, ó sì mú kùlọ̀bù náà dé òpin ìdíje Ife-ẹ̀yẹ Africa Club Champions. Wọ́n kùnà ayò òpin lọ́wọ́ Zamalek láti Egypt.

Festus Onigbinde
Personal information
OrúkọFestus 'Adegboye' Onigbinde
Ọjọ́ ìbí5 Oṣù Kẹta 1938 (1938-03-05) (ọmọ ọdún 86)[1]
Ibi ọjọ́ibíModakeke, Osun State, Nigeria
Teams managed
YearsTeam
1981–1984Nigeria
2002Nigeria


Àwọn ìtọ́kasí àtúnṣe

  1. "Festus Onigbinde (ogol.com.br)". ogol.com.br. Retrieved 2015-01-20. 
  2. Manaschev, Erlan (2008-07-03). "World Cup 2002 - Match Details". RSSSF. Retrieved 2009-10-07.