Ishaya Bako tí a bí ní ọjọ́ ọjọ́gbọ̀n Oṣù kejìlá ọdún 1986 jẹ́ olùdarí fíímù Nàìj́iríà àti òǹkọ̀wé fíimù.[1]

Ishaya Bako
Ọjọ́ìbíOṣù Kejìlá 30, 1986 (1986-12-30) (ọmọ ọdún 37)
Kaduna
Orílẹ̀-èdèNigerian
Ọmọ orílẹ̀-èdèNigerian
Ẹ̀kọ́Covenant University, London Film School
Iṣẹ́Nigerian film director and screenwriter
Gbajúmọ̀ fúnHis film Fuelling Poverty
Notable workFuelling Poverty

Ìbẹ̀rẹ̀ ìgbésí-ayé ẹ̀ àtúnṣe

Ìlú Kaduna ni wọ́n bí i, níbi tó ti gbé ní gbogbo ayé rẹ̀ tó sì tún padà lọ sí ìlú Lọ́ńdọ̀nù, níbi tó ti kàwé ní Ilé-ẹ̀kọ́ Fíìmù Lọ́ńdọ̀nù.

Iṣẹ́-ṣíṣe àtúnṣe

Lẹ́yìn tí ó lọ sí Ilé-ẹ̀kọ́ Fíímù ti Ìlú Lọ́ńdọ̀nù, Bako tẹ̀síwájú sí ìwé àfọwọ́kọ àti ṣe ìdarí Awards Africa Movie Academy Awards (AMAA) tí ó gba Braids on a Bald Head. Ó jáwé olúborí fún Àwọn Ẹ̀bùn Fíímù Kúkúrú Tí ó dára jùlọ ní 8th Africa Movie Academy Awards. Ó jẹ́ ohùn tí ó ń yọjú tàbí dìde ní ti ìran rẹ̀ àti ọmọ ẹgbẹ́ kan tí a yàn èyiun Global Shapers, ìkójọpọ̀ àwọn aláfojúsùn ọ̀dọ́ tí ó bẹ̀rẹ̀ nípasẹ̀ World Economic Forum.[2]

Fíìmù rẹ̀, Fueling Poverty, ìwé ìtàn lórí òsì àti owó-ìrànlọ́wọ́-lórí-epo ní Nàìjíríà, jẹ́ ohun tí onímọ̀-lítírésọ̀ Wọlé Ṣóyínká jẹ́ asọ̀tàn rẹ̀. Ó ń gbé ní olú-ìlú Nàìjíríà Abuja, FCT.[3] Fíìmù rẹ̀ The Royal Hibiscus Hotel ni a ṣe àfihàn ní 2017 Toronto International Film Festival.

Ó tún jẹ́ ọ̀kan nínú àwọn òǹkọ̀wé fún fíímù Lionheart (fíìmù ọdún 2018).[4]

Àwọn ìtọ́kasí àtúnṣe