Joseph Òkéfọláhàn Ọdúnjọ je olukowe omo ile Naijiria

Joseph Okefolahan Odunjo

Lítírṣọ̀ adíláwọ̀ ti di ìlúmọ̀miká báyìí; ó ti gbayi ni ilé; ó ti gbayì lóko bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ó ti gba iyì ní ìdálẹ̀ ju ilé lọ. Ọ̀pọ̀ òyìnbó ni ó ti fi ọ̀rọ̀ ìjìnlẹ̀ lítíréṣọ̀ adúláwọ̀ gboyè ìjìnlẹ̀ ìwé, pupọ ninu awọn ọmọ adúláwọ̀ lo si ti di olówó àti olórúkọ nipa fifi èdè àjòjí bi èdè Gẹ̀ẹ́sì kọ ìwé lítíréṣọ̀ adúlawọ̀. Nínú wọn ni Amos Tutuola, Chinua Achebe, Àlùkò, Nwankwo ati Wole Soyinka.

Orí Kẹta: “Àgbéyẹ̀wò Àwọn Ìwé Alákọ̀ọ́bẹ̀rẹ̀ Yorùbá Láti Ìbẹ̀rẹ̀ Pẹ̀pẹ̀” - Ojú-Ìwé 101-131. Olúdáre Ọlájubù. àtúnṣe

Ọ̀rọ̀ Àkọ́sọ

O ti tó ọdún mẹ́ẹ̀dógún (láti 1970) tí mo ti ń ṣiṣẹ́ ìwádìí nípa àwọn ìwé kika fun Alákọ̀ọ́bẹ̀rẹ̀ Yorùbá. Mo lo ọ̀pọ̀ àwọn ìweé ti a darúkọ nínú iṣẹ yìí yàlà gẹ́gẹ́ bí alákọ̀ọ́bẹ̀rẹ̀ funraami, gẹ́gẹ́ bí olùkọ́ ní ilé ẹ̀kọ́ alákọ̀ọ́bẹ̀rẹ̀ àti gẹ́gẹ́ bí ẹni ti ń tanná wá ìmọ̀.

Orí Kẹrin: “Aáyan Àwọn Òǹkọ̀wé Ìtàn-àròsọ Yorùbá Láti Àárọ̀ Ọjọ́ Títí Di Ọdún Òmìnira (1960)” Ojú-Ìwé 132-150. Afọlábí Ọlábọ̀dé. àtúnṣe

Ẹni tí ó ba ẹran eerinlórí àtẹ, ko le mọyì eerin, ni ọrọ ìtàn-àròsọ Yorùbá jẹ fún ọpọlọpọ ènìyàn lode òní. Nígbà tí a bá sì wo orí àtẹ lọjọ òní ti a le tọ́ka sí ìwé ìtàn-àròsọ ogún, ọgbọ̀n tàbí ju bẹ́ẹ̀ lọ, tí a ń ṣà, tí a ́ rọ̀, ti a ń sọ pé a fẹran ọ̀kan tàbí a yan ọkan ni ìpọ̀sì, nítori pé wọ́n wà ni. Èyí nikan ki ọna ti awa òǹkàwé òde-òní fi máa ń yunra.

Iwwe ti a yewo àtúnṣe

  • Ọlatúndé O. Ọlátúnji (1988) Ìdàgbàsokè Ẹ̀kọ́ Ìmọ̀ Ìjìnlẹ̀ Yorùbá (Odunjo Memorial Lecture Series). Estorise Nigeria Limited.
  • J.F. Ọdunjọ (2001) Ọmọ Òkú Ọ̀run Ibadan; African Universities Press ISBN 978-148-009-2. Ojú-iwé 54.