Kola Oyewo (bìi ní ọjọ́ kẹrìndínlọ́gbọn Oṣù kẹta 1946) jẹ́ òṣèré àti olùkọ́ ọmọ orìlé èdè Nàìjírìà

Kola Oyewo
Ọjọ́ìbí(1946-03-27)27 Oṣù Kẹta 1946
Orílẹ̀-èdèorìlé èdè Nàìjírìà
Ọmọ orílẹ̀-èdèorìlé èdè Nàìjírìà
Iṣẹ́
  • Òṣèré
  • Olùkọ́
Gbajúmọ̀ fúnThe Gods Are Not To Blame and Sango (1997)

Ìgbà èwe àtúnṣe

A bìi ní ọjọ́ kẹrìndínlọ́gbọn Oṣù kẹta 1946 ní ìlú Ọ̀bà ilé ti ìlú Ọ̀ṣun gúúsù-wọ̀orùn Nàìjírìà.[1]

Ètò ẹ̀kọ́ àtúnṣe

Ó lọ sí ilé ẹ̀kọ́ gíga ti Obáfẹ́mi Awólọ́wọ̀ Yunifásitì níbi tí ó ti gba ìwé ẹ̀rí nínu ìmo eré ìtàgé kí ó tó gba oyè kínín (B. A) nínu ìmọ tíátà ní Yunifásitì kan náà ní ọduń 1995. Ó tẹ̀síwájú nínu ẹ̀kọ́ rẹ̀ ní Yunifásitì ti ìlú Ìbàdàn níbi tí ó ti gba oyè kejì (M. A) àti ìkẹta (Ph. D) ní ìmọ eré ìtàgé.

Iṣẹ́ àtúnṣe

Ó bẹ̀ẹ̀rẹ̀ eré ṣíṣe ní odún 1964 lẹ́yìn tí ó darapọ̀ mọ́ ẹgbẹ́ òṣèré Oyin Adéjọbí. Ipa tí ó kọ́kọ́ kó ni Adéjàre nínú eré Orogún Adédigba, èyí tí ó jẹ́ ìgbésí ayé Oyin Adéjọbí.[2] Lẹ́yìn tí ó lo ọdún mẹ́ẹ́san pẹ̀lú Oyin Adéjọbí, ó darapọ̀ mọ́ egbé tíátà Yunifásitì ilé ifẹ̀ níbi tí ó tí bá olóyè Olá Rótìmí, tí ó jẹ́ òṣèré àti olùkọ́ ṣisẹ́. Wọ́n mọ Kola Oyewo sí Ọdẹ́ wálé, ipa tí ó kó nínu The Gods Are not to Blame, eré tí Olá Rótìmí kọ.

Ní odún 1996, ó darapọ̀ mọ́ ilé ẹ̀kọ́ gíga ti Obáfẹ́mi Awólọ́wọ̀ Yunifásitì bí olúkọ́, ó sì dí àgbà olùkọ́ kí ó tó fẹ̀hìntí ní Oṣù kesań 2011.[3] Lẹ́yìn tí ó fẹ̀hìntì, ó darapọ̀ mọ́ Yunifásítì Reedemers, níbi tí ó ti jẹ́ olórí olùkó ẹ̀ka eré ṣíṣe[4]

In 1996, he joined the services of Yunifásítì Ọbáfẹ́mi Awólọ́wọ where he rose to the rank of a senior lecturer before he retired in September 2011.[5] After his retirement from Obafemi Awolowo University, he joined the services of Redeemer's University, where he currently serves as head of the department of dramatic art.[6]

Àwọn eré àtúnṣe

  • Sango (1997)
  • Super story (episode 1)
  • The Gods Are Not To Blame

Àwọn ìtọ́kasí àtúnṣe