Nicole Amarteifio (tí a bí ní ọdún 1982) jẹ́ agbéréjáde, olùdarí àti ònkọ̀tàn eré ọmọ orílẹ̀-èdè Ghánà.

Nicole Amarteifio
Ọjọ́ìbí1982 (ọmọ ọdún 41–42)
Orílẹ̀-èdèGhanaian
Iléẹ̀kọ́ gígaBrandeis University
Georgetown University
Iṣẹ́Film director, producer, screenwriter
Ìgbà iṣẹ́2012–present

Ìsẹ̀mí rẹ̀ àtúnṣe

A bí Amarteifio ní orílẹ̀-èdè Ghánà ṣùgbọ́n ó gbé ní Ìlú Lọ́ndọ̀nù fún ọdún mẹ́fà láti ìgbà tí ó fi wà lọ́mọ oṣù mẹ́ta nítorí ìfipágbàjọba tí ó ṣẹlẹ̀ ní orílẹ̀-èdè rẹ̀.[1] Ó padà tún kúrò ní ìlú Lọ́ndọ̀nù pẹ̀lú ẹbí rẹ̀ láti lọ gbé ní agbègbè Scarsdale ní ìlú New York, ṣùgbọ́n ó maá n lọ sí orílẹ̀-èdè Ghánà lọ́dọọdún láti lo àwọn àsìkò ìsinmi rẹ̀.[2] Àwọn òbí Amarteifio padà sí orílẹ̀-èdè Ghánà ní ọdún 1997. Ó gba oyè-ẹ̀kọ́ nínu ìmọ̀ nípa àwọn ẹ̀yà aláwọ̀dúdú láti ilé-ẹ̀kọ́ gíga Brandeis University ní ọdún 2004.[3] Lẹ́hìn ìparí ẹ̀kọ́, ó rí iṣẹ́ sí ilé-iṣé Whitaker Group, èyí tí ó wà ní Washington,DC gẹ́gẹ́ bi alámọ̀ràn fún ìdàgbàsókè ètò ọrọ̀-ajé Áfíríkà.[4]

Ní ọdún 2006, Amarteifio lọ sí Accra, orílẹ̀-èdè Ghana láti ṣiṣẹ́ ìdàgbàsókè ọrọ̀-ajé. Láìpẹ́jọjọ sí ìgbà náà, ó ní ìròrí láti ṣe ìbádógba eré Sex and the City ní ìlú Accra.[5] Amarteifio padà sí orílẹ̀-èdè Amẹ́ríkà láti lọ kẹ́kọ̀ọ́ ìmọ̀ ìbaráẹnisọ̀rọ̀ ní ilé-ẹ̀kọ́ gíga Georgetown University ó sì gba oyè-ẹ̀kọ́ gíga ní ọdún 2010.[1] Nígbà tí ó fi wà ní ìlú Georgetown, ó kẹ́kọ̀ọ́ lábẹ Mike Long, ẹnití ó gbàá níyànjú láti máa ṣiṣẹ́ ìfẹ́ ọkàn rẹ̀ gẹ́gẹ́ bi ònkọ̀tàn eré.[6] Amarteifio gba iṣẹ́ ilé ìfowópamọ́ àgbáyé, èyí tí ó mú kí ó padà sí ìlú Accra. Lẹ́hìn oṣù mélòó kan tí ó padà sí Ghánà, ó bẹ̀rẹ̀ sí ní fi ìròrí eré rẹ̀ tó àwọn òṣìṣé eré tẹlifíṣọ̀nù létí. Wọ́n kọ̀ láti gba iṣẹ́ náà ṣùgbọ́n wọ́n gbàá níyànjú láti kọ́ bí a ṣé n kọ ìwé eré.[7]

Àṣàyàn àwọn eré rẹ̀ àtúnṣe

  • 2012: Praying for Daylight (short film; writer and co-producer)
  • 2014–present: An African City (TV series; writer, co-director, producer)
  • 2016: The Republic (TV series; writer, director, producer)
  • 2018: Before the Vows (writer, director, producer)
  • 2020: Indie Nation (as herself)

Àwọn ìtọ́kasí àtúnṣe

  1. 1.0 1.1 Rao, Mallika (22 September 2016). "Meet the Shonda Rhimes of Ghana". https://www.marieclaire.com/culture/a22729/shonda-rhimes-of-ghana-nicole-amarteifio/. Retrieved 8 October 2020. 
  2. Gardner, Laura (2017). "Sex and the African City". Brandeis University. Retrieved 8 October 2020. 
  3. Gardner, Laura (2017). "Sex and the African City". Brandeis University. Retrieved 8 October 2020. 
  4. "Nicole Amarteifio — Creator, An African City Web Series". Medium.com. 5 November 2014. Retrieved 8 October 2020. 
  5. Gardner, Laura (2017). "Sex and the African City". Brandeis University. Retrieved 8 October 2020. 
  6. "Nicole Amarteifio — Creator, An African City Web Series". Medium.com. 5 November 2014. Retrieved 8 October 2020. 
  7. Gardner, Laura (2017). "Sex and the African City". Brandeis University. Retrieved 8 October 2020. 

Àwọn ìtakùn Ìjásóde àtúnṣe