Nnorom Azuonye

Onkọ̀wé

Nnorom Azuonye tí a bí ní ọjọ́ kejìlá oṣù keje ni ìpínlè Abia ti orílẹ̀-èdè Nàìjíríà jẹ́ òǹkọ̀wé, adarí eré orí ìtàgé, òǹkọ̀tàn àti akéwì. Ó tún jẹ́ oníwàásù ní ìjọ Methodist ní ìlú Britain. Àwọn ìwé tí ó ti kọ ni Letter to God & Other poems ní ọdún 2003, The Bridge Selection: Poems for the road ní ọdún 2005 & 2012 àti Funeral of the Minstrel ní ọdún 2015. Òun ni olùdarí àti alágbàátẹrù SPM Publications Ltd. Òun náà ni olùdásílẹ̀ àti alábòójútó Sentinel Poetry Movement tí ó sì tún jẹ́ olùdásílẹ̀ àti òǹtẹ̀wé magasíìnì Nollywood Focus, Sentinel Literary Quarterly, Sentinel Nigeria àti Sentinel Champions.[1][2]

Àwọn Ìtọ́kasí àtúnṣe

  1. "Nnorom Azuonye - About me". www.nnoromazuonye.com. Archived from the original on 2016-03-03. Retrieved 2018-01-02. 
  2. "African-Writing Online; Poetry; Nnorom Azuonye". African Writing Magazine; Many Literatures, One Voice; Home page, Issue No 11. Retrieved 2019-12-27.