Peju Alatise jẹ ayàwòrán ilẹ̀ Nàìjíríà, akẹ́wì, òǹkọ̀wé, àti ọ̀kan lára àwọn òṣìṣẹ́ ni National Museum of African Art, tí ó jẹ́ ọ̀kan lára ẹ̀yà Smithsonian Institution. Ọdún 1975 ni wọ́n bí Alatise sí ìdílé mùsùlùmí òdodo ní Ìlú Èkó.[1]

Peju Alatise
Ọjọ́ìbíÀdàkọ:Bya
Lagos, Nigeria
Iṣẹ́Multimedia artist
Awards2017 FNB Art Prize

Ilé-ìwé Ladoke Akintola University ní ìpínlẹ̀ Oyo, orílẹ̀-èdè Nàìjíríà. Lẹ́yìn ìwé rẹ̀, ó ṣiṣẹ́ fún ogun ọdún ní ile-iṣẹ́ kan gẹ́gẹ́ bí ayàwòrán[2].

Wọn pàtẹ àwọn àwòrán iṣẹ́ rẹ̀ nínú àtúṣe tuntun ẹlékẹtàdínlọ́gọ́ta ti Venice Biennale (57th edition) tí àkọ́lé rẹ̀ ń jẹ́ Viva Arte Viva (Kí iṣẹ́ ọnọ̀ pé kánri-kése ).[3][4] Alatise pẹ̀lú àwọn ọmọ orílẹ̀-èdè Nàìjìríà méjì mìíràn Victor Ehikhamenor àti Qudus Onikeku ni wọ́n jẹ́ ọmọ Nàìjìríà àkọ́kọ́ ti yóò ni àǹfàní láti wà ni ìpàtẹ iṣẹ́-ọnọ̀ náá[5]. Àwòrán rẹ̀ dálé ìgbé ayé ọmọ ọ̀dọ̀ obìrin.[1]

Alatise gba àmì-ẹ̀yẹ FNB Art Prize ní ọdún 2017.[6]

Alatise gbé oríyìn fún ayàwòrán David Dale, Bruce Onabrakpeya, Nike Monica Davies, Susanna Wenger, Nàìjìríà àti àṣà Yoruba gẹ́gẹ́ bí ohun ìwúrí fún iṣẹ́ òun.

Àwọn ìtọ́kasí àtúnṣe

  1. 1.0 1.1 "Meet Peju Alatise, Qudus Onikeku & Victor Ehikhamenor – Artists at Nigeria's Debut at the 57th Venice Biennale". 27 March 2017. 
  2. "Peju Alatise: Nigerian artist-painter" (in en-GB). Afroculture.net. http://afroculture.net/peju-alatise-nigerian-artist-painter/. 
  3. "Nigerian arts make historical appearance in Venice - Vanguard News". 3 April 2017. 
  4. "Nigerian visual art set to make history at the Venice Biennale". 16 March 2017. Archived from the original on 20 May 2019. Retrieved 2 August 2022. 
  5. Kabov, Valerie. "Viva Africa Viva!- Africa at the 57th Venice Biennale". ArtAfrica. Retrieved 11 June 2019. 
  6. "Peju Alatise Wins FNB Art Prize 2017" (in en-US). ArtThrob. 15 August 2017. https://artthrob.co.za/2017/08/15/peju-alatise-wins-fnb-art-prize-2017/.