Yẹmí ṣóladé (tí wọ́n bí ní Ọjọ́ kọkànlélọ̀gbọ̀n oṣù kìíní ọdún 1960) jẹ́ gbajúmọ̀ àti arẹwà ọmọkùnrin òṣèré sinimá àgbéléwò ọmọ bíbí orílẹ̀ èdè Nàìjíríà.[1]

Ìgbà èwe àti aáyan ìkẹ́kọ̀ọ́ rẹ̀ àtúnṣe

Gẹ́gẹ́ bí a ti sọ ṣáájú, wọ́n bí Yẹmí ṣóladé lọ́jọ́ kọkànlélọ̀gbọ̀n oṣù kìíní ọdún 1960 sí ìlú Èkó lorílẹ̀-èdè Nàìjíríà . Nígbà èwe rẹ̀, ó kàwé ní St. Thomas Aquilla Primary School àti Birch Freeman Secondary school, ní Sùúrùlélrè, ní ìpínlẹ̀ Èkó lórílẹ̀ èdè Nàìjíríà. Lẹ́yìn èyí, Yemi fò gẹ̀ẹ̀rẹ̀, ó dèrọ̀ ìlú Ọba níbi tí ó ti tẹ̀ síwájú nínú ẹ̀kọ́ rẹ̀ tí ó sìn gba ìwé ẹ̀rí A Level ni ilé-ìwé gíga Tyhill College ní ìlú Coventry lorílẹ̀ èdè Gẹ̀ẹ́sì. Lẹ́yìn èyí, ó tún padà sí orílẹ̀-èdè Nàìjíríà, ó sìn tẹ̀ síwájú nínú ẹ̀kọ́ rẹ̀ ní Oyo State College of Arts and Science, OSCAS. Lẹ́yìn náà ó tún kẹ́kọ̀ọ́ gboyè sí i nínú iṣẹ́ tíátà ní Obafemi Awolowo University (OAU), ní Ilé-Ifẹ̀ìpínlẹ̀ Ọ̀ṣun.[2] [3] [1] [4]

Àwọn Ìtọ́kasí àtúnṣe

  1. 1.0 1.1 "All You Need To Know And More About Yemi Solade (Biography) - Playground.ng". Playground.ng. 2017-01-31. Archived from the original on 2019-12-10. Retrieved 2019-12-10. 
  2. Published (2015-12-15). "My first wife left me, says Yemi Solade". Punch Newspapers. Retrieved 2019-12-10. 
  3. "Yemi Solade: 13 facts you should know about the Nollywood actor - Nigerian Entertainment Today". Nigerian Entertainment Today. 2016-02-01. Retrieved 2019-12-10. 
  4. "Yemi Solade wears new look - The Nation Newspaper". The Nation Newspaper (in Èdè Latini). 2019-07-12. Retrieved 2019-12-10.