Adedotun Aremu Gbadebo III

Alake ti Ile Egba

Adedotun Aremu Gbadebo lll (tí a bí ní ọjọ́ kẹrìnlá oṣù kẹsan ọdún 1943) ní Aláké ti ilẹ̀ Ẹ̀gbá lọwọlọwọ bayi. Ẹ̀gbá jẹ́ ẹ̀yà kan ní ìlú [[Abẹ́òkuta]], orílẹ̀ èdè Nàìjíríà. Ó ti wà lórí oyè láti ọjọ́ kejì oṣù kẹjọ ọdún 2005.

Alake

Adedotun Gbadebo
Alake of Egba
Lọ́wọ́lọ́wọ́
Ó gun orí àga
2 August 2005
AsíwájúOba Oyebade Lipede
Àwọn àlàyé onítòhún
Ọjọ́ìbí14 Oṣù Kẹ̀sán 1943 (1943-09-14) (ọmọ ọdún 80)
Abeokuta

Ìbẹ̀rẹ̀ Ayé àtúnṣe

A bí Gbádébọ̀ ní ọjọ́ kẹrìnlá oṣù kẹsan ọdún 1943 sínú ìdílé ọba ti Láarún. Ó jẹ́ ọ̀kan lára àwọn ọmọ-ọmọ Aláké kẹfà ti ìlú Ẹ̀gbá, Ọba Gbádébọ̀, ẹni tí ó wà lórí oyè láti ọdún 1898 títí di ọdún 1920, Ó tún jẹ́ arákùnrin Ọba Gbádébọ̀ ll.[1]

Gbádébọ̀ lọ sí ilé-ẹ̀kọ́ giga Baptist BoysAbẹ́òkuta àti ile iwe Grammar Ibadan tí ó wà ní ìlú Ìbàdàn. Ó tún tẹ̀ siwaju láti lọ sí ilé-ẹ̀kọ́ gíga Yunifásítì Ibadan ní ọdún 1965, níbití ó ti gba oyè àkọ́kọ́ ninu ìmọ̀ Arts ní ọdún 1969.[2] Ó darapọ̀ mọ́ iṣẹ́ ológun ní ọdún 1969. Ó sì lọ sí ilé-ẹ̀kọ́ àwọn ológun ti Command and Staff College tí ó wà ní Jaji láti oṣù kẹsan ọdún 1978 títí di oṣù kẹjọ ọdún 1979. Níkẹ̀hìn, Ó di ọ̀kan lára àwọn òṣìṣẹ́ àgbà sí ọ̀gágun Tunde Idiagbon, ẹnití ó jẹ́ olórí òṣìṣẹ́ ní olú ilé iṣẹ́ ti Baraki ologun, láti oṣù kíní ọdún 1984 títí di oṣú kẹsan ọdún 1985. Ó fẹ̀hìntì nínú iṣẹ́ ológun gẹ́gẹ́ bii Kononeli.[3]

Ìdìbò àtúnṣe

Ìdìbò yan Gbádébọ̀ gẹ́gẹ́ bi Aláké ní oṣù kẹjọ ọdún 2005 gba oṣù mẹ́fà gbakó nítorí àìní ìdánilójú lori tani yíò rọ́pò Aláké ti tẹ́lẹ̀, Ọba Oyebade Lipede, tí ó wàjà ní ọjọ́ kẹta oṣù kejì ọdún 2005[4]. Gbádébọ̀ ní ìbò mẹ́ẹ̀dógún nínú àwọn ìbò mẹ́tàlélógún látàrí ètò ìdìbò yàn tí àwọn afọbajẹ ti ìlú Ẹ̀gbá gbé kalẹ̀, níbití ó ti borí àwọn mẹjọ tí wọn n ba díje, èyí tí Adeleke àbúrò rẹ jẹ́ ọ̀kan lára wọn.[5]

Àríyànjiyàn àtúnṣe

Ní oṣù kẹrin ọdún 2010, wọ́n gbé àríyànjiyàn laarin Gbádébọ̀ àti Olú ti Ìgbẹ̀hìn , Ọba Festus Oluwọle Makinde lọ sí ilé ẹjọ́ gíga ti Ìpínlẹ̀ Ògùn, ẹ̀ka ìdájọ́ ti Abẹ́òkuta, Ìpínlẹ̀ Ògùn, Nàìjíríà. Olú ti Ìgbèyìn n sọ nípa ìgbìnyànjú Aláké láti yí oyè oun padà láti Olú ti Ìgbèyìn sí Olú ti Mòwé. Ó ní àyípadà yí yíò kó ipa tí ó lòdì sí ètọ́ òun láti lo àwọn ààmì Ìbílẹ̀ kan lára wọn ni ọ̀pá àse ti Ìgbèhìn.

Àwọn Ìtọ́kasí àtúnṣe

  1. https://www.thepointng.com/oba-adedotun-aremu-gbadebo-the-alakes-75-years-story/
  2. Moses, Peter (2018-09-23). "Glamour as Alake of Egbaland marks 75th birthday – Daily Trust". Daily Trust. Archived from the original on 2020-01-27. Retrieved 2020-01-27. 
  3. "Oando chair, Company Secretary, GM Operations receives prestigious recognitions". Premium Times Nigeria. 2019-11-01. Retrieved 2020-01-27. 
  4. "Gbadebo emerges new Alake - • We’re yet to confirm any candidate — Ogun govt". OnlineNigeria.com. Retrieved 2020-01-27.  C1 control character in |title= at position 29 (help)[Ìjápọ̀ tí kò ṣiṣẹ́ mọ́]
  5. https://allafrica.com/stories/200508040831.html