Ọdarawu fìgbà kan jẹ́ Aláàfin Ìlú Ọ̀yọ́, ní sẹ́ńtúrì kẹtàdínlógún.[1] Òun ni Aláàfin àkọ́kọ́ tí àwọn Ọ̀yọ́ Mèsì ò tẹ́wọ́gbà.[1]

Ọdarawu jẹ́ ọmọ Aláàfin Àjàgbó. Kò pẹ́ rárá lórí oyè. Ó jẹ́ onínú fùfù, tó máa ń tètè bínú. Gẹ́gẹ́ bí ìtàn ṣe sọ, ìbínú rẹ̀ ló sun dé bí wọ́n ṣe le kúrò lórí oyè, tí ó sì dúró gẹ́gẹ́ bí ẹ̀kọ́ fún àwọn ọba tó jẹ lẹ́yìn rẹ̀. Ogun tí Ọdarawu kópa nínú rẹ̀ ni èyí tó ṣe kẹ́yìn. Lásìkò ìjọba rẹ̀, ó pàṣẹ kí wọ́n ba ọjà kan jẹ́. Orúkọ ọjà yìí ni Ojo-segi, nítorí ọkàn lára àwọn tó ń tajà níbẹ̀ ṣèṣì gbá Aláàfin yìí létí láìmọ̀ pé òun ni Aláàfin, tí ó sì tún pè é ní olè.[2] Lẹ́yìn gbogbo awuyewuye yìí, àwọn ará Ọ̀yọ́ ní kó ṣígbá wò, nítorí kò yẹ láti ṣèjọba ìlú Ọ̀yọ́.

Lẹ́yìn tó wàjà, Aláàfin Kánran jẹ oyè Aláàfin.

Àwọn ìtọ́kasí

àtúnṣe
  1. 1.0 1.1 Law, R. C. C. (1971). "The constitutional troubles of Ọyọ in the eighteenth century". The Journal of African History 12 (1): 25–44. doi:10.1017/s0021853700000050. ISSN 0021-8537. 
  2. Johnson, Samuel (2010), "Origin and Early History", The History of the Yorubas, Cambridge University Press, pp. 3–14, ISBN 9780511702617, doi:10.1017/cbo9780511702617.006