Christie Ade Ajayi (tí a bí ní ọdún 1930) jẹ́ ọmọ orílẹ̀-èdè Nàìjíríà tí ó ń jà fitafita fún kíkó àwọn ọmọdé bí a ti ń kàwé láti ìgbà tí wón ti wà ní ọmọ jòjòló. Ó ti kọ ọ̀pọ̀lọpọ̀ ìwé ní èdè Gẹ̀ẹ́sì fún àwọn ọmọdé, àwọn ìwé rẹ̀ sì jẹ́ ìwé nípa Nàìjíríà. Ó tún jẹ́ olùkọ́ fún ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọdún, ó s jẹ́ ọmọ àwọn ẹgbẹ́ kọ̀kan tí ó ń bìkítà fún ètò ẹ̀kọ́ àwọn ọmọdé.

Christie Ade Ajayi
Ọjọ́ìbíChristie Aduke Martins
13 Oṣù Kẹta 1930 (1930-03-13) (ọmọ ọdún 94)
Ile Oluji, Ìpínlẹ̀ Ondo, Nàìjíríà
Orílẹ̀-èdèNàìjíríà
Olólùfẹ́J. F. Ade Ajayi

Ìtàn àtúnṣe

Wọ́n bí Christie Aduke Martins ní ọjọ́ kẹtàlá oṣù kẹta ọdún 1930 ní Ile Oluji, Ìpínlẹ̀ Òndó, Christie Ade Ajayi (tí wón tún le ko bi Ade-Ajayi) lọ sí Kudeti Girls' School ní ìlú Ibadan (tí àwọn ènìyàn wá padà mọ̀ sí St. Anne's School), lẹyìn náà, ó lọ sí United Missionary College, Ibadan níbi tí ó ti kẹ́kọ̀ọ́ láti di olùkọ́.[1] Ó tún tẹ ẹ̀kọ́ rẹ̀ síwájú ní Froebel Institute, London[2] àti ní Institute of Education níbi tí ó ti gba àmì-ẹ̀yẹ Diploma nínú ìmò títọ́ àwọn ọmọdé ní ọdún 1958.[1] Láàrin ọdún 1952 sí 1978, ó kọ́ àwọn ní ọ̀pọ̀lọpọ̀ ilé-ìwé ní Nàìjíríà àti ní ilé-ìwé kan ní London, níbi tí ó ti di olórí ilé-iwé náà headmistress,[3] Ó tún tẹ ẹ̀kọ́ rẹ̀ síwájú ní San Jose State University, California.[1] Ó fẹ́ J. F. Ade Ajayi ní ọdún 1956, àwọn méjèèjì sí bí ọmọ márùn-ún[4]

Àwọn Ìtọ́kasí àtúnṣe

  1. 1.0 1.1 1.2 Henrietta C. Otokunefor, Obiageli C. Nwodo, Nigerian Female Writers: A Critical Perspective, Malthouse Press 1989, pp 99-100
  2. Philomena Osazee Esigbemi Fayose, Nigerian Children's Literature in English, AENL Educational Publishers, p70
  3. Kunle Ifaturoti, Tinu Ifaturoti, To have and to hold, NPS Educational, 1994, p250
  4. [https://www.theguardian.com/books/2014/sep/10/jf-ade-ajayi JF Ade Ajayi obituary in The Guardian, 10 Sep 2014