Velekete Slave Market: Ìyàtọ̀ láàrin àwọn àtúnyẹ̀wò

Content deleted Content added
blank content for move to earlier page with YO name on same topic; make #REDIRECT
Àlẹ̀mọ́: New redirect
 
Ìlà 1:
#REDIRECT: [[Ọjà Ẹrù Veléketé]]
[[File:SLAVE MARKET, Lagos.tif|Slave Market, Badagry|thumb|270px|right]]
'''Velekete ọjà ẹrú''' ni ọjà ará tí ó wà ní ìlú [[àgbádárìgì]], ní [[Ìpínlẹ̀ Èkó]].<ref>{{cite book|author=Hakeem Ibikunle Tijani|title=The African diaspora: historical analysis, poetic verses, and pedagogy|url=https://books.google.com/books?id=fdFPAQAAIAAJ|year=2010|publisher=Learning Solutions|isbn=978-0-558-49759-0}}</ref> Wọ́n da ọjà òwò ẹrú yí sílẹ̀ ní ọdún 1502, wọ́n sọ orúkọ ọjà yí ní Velekete tí ó jẹ́ orúkọ òrìṣà [[omi]] ati afẹ́fẹ́.<ref>{{cite book|author1=A. Babatunde Olaide-Mesewaku|author2=Babatunde A. Olaide-Mesewaku|title=Badagry district, 1863-1999|url=https://books.google.com/books?id=aJMuAQAAIAAJ|year=2001|publisher=John West Publications Ltd.|isbn=978-978-163-090-3}}</ref>Ọjà yí gbajúmọ̀ gidi ní àsìkò owó ẹrú káàkiri [[Atlantic slave trade|Trans-Atlantic Slave trade]], ó sì tún jẹ́ ojúkojú tí àwọn abáni rẹrú ti ma ń dúná dúrá pẹ̀lú olówó ẹrú tí ó f2lẹ́ ta ará fún àwọn Gẹ̀ẹ́sì, èyí mú kí ọjà yí gbajúmọ̀ káàkiri ilẹ̀ Ìwọ̀ Oòrùn Áfíríkà.<ref>{{cite news|url=http://www.vanguardngr.com/2013/02/vlekete-when-a-slave-market-becomes-a-tourist-centre/|title=Vlekete: When a slave market becomes a tourist centre|work=[[Vanguard (Nigeria)|Vanguard Newspaper]]|last=Njoku|first=Jude|date=6 February 2013|accessdate=16 January 2016}}</ref>
 
== Bí ó ṣe bẹ̀rẹ̀ ==
Dídé tí ọ̀gbẹ́ni kan olówò ẹrú tí ó jẹ́ ọmọ orílẹ̀-èdè Dutchland tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ ''Hendrik Hertog'' tí wọ́n sábà ma ń da pe ní ''Yoo Huntokonu'' dé sí ìlú agbádárìgì ni ó gba àwọn lààmì-laaka ọmọ onílẹ̀ níyànjú pe kí wọ́n dá [[ọjà]] tí wọn yóò w ti ma ta àwọn ẹrú wọn, wọ́n sì da ọjà náà sílẹ̀ tí wọ́n pèé ní ''Velekete''. Ó gba ilẹ̀, ó sì di dá ọjà yí sílẹ̀ tí àwọn olówò-ẹrú bíi tìrẹ̀ sì wá ń fi àwọn ohun tí wọ́n ní ṣe pàṣípàrọ̀ fún ọmọ èèyan gẹ́gẹ́ bí ará. Èyí kò ṣàdédé rí bẹ́ẹ̀ bí kò ṣe wípé àwọn olóyè ati àwọn alẹ́nu-lọ́rọ̀ àwùjọ ń rọ́wọ́ pọ́n lá níbi okòwò náà. Ọjà yí gbèrú nígbà tí àwọn òntajà àti ònrajà ti gbọ́ ara wọn yé, tí wọ́n sì ti mọ adùn tí ó wà nínú òwò wọn ati bí awọn aláwọ̀ funfun ṣe nílò òṣìṣẹ́ sí nínú oko [[ìrèkè]] wọn.<ref>{{Cite web|date=2018-07-19|title=The dark history of the Nigerian colonial town of Badagry, one of Africa's first slave ports|url=https://face2faceafrica.com/article/the-dark-history-of-the-nigerian-colonial-town-of-badagry-one-of-africas-first-slave-ports|access-date=2021-08-19|website=Face2Face Africa|language=en}}</ref>
 
== Àwọn ìṣẹ̀lẹ̀ mále gbàgbé tí ó ti wáyé níbẹ̀ ==
[[File:Canon at Badagry slave market.jpg|thumb|Canon at Slave Market, Badagry]]
Ní ọdún 1805, àwọn èèbó gẹ̀ẹ́sì mú Scipio Vaughan ẹni tí ó jẹ́ ará ìlú [[Òwu]] lẹ́rú, wọ́n sì kó òun àti àwọn mélòó kan tí wọ́n jọ kó lẹ́rú pọ̀ lọ tà ní ọjà Velekete ní ìlú àgbádárìgì, tí wọ́n sì gba ibẹ̀ di ẹrú ní ilẹ̀ [[Amẹ́ríkà]].<ref name="Bamidele 2020">{{cite web|last=Bamidele|first=Michael|date=2020-02-09|title=Back-To-Africa: A Dying Wish Births A Living Legacy|url=https://guardian.ng/life/back-to-africa-a-dying-wish-births-a-living-legacy/|access-date=2021-08-05|website=The Guardian Nigeria News - Nigeria and World News}}</ref> Wọ́n tún ma ń kó àwọn ẹrú lótíṣiríṣi wà láti àwọn ìlú bí ibintí a mọ̀ sí [[Ìpínlẹ̀ Abia]] lóní wá tà ní ọjà Velekete. Wọ́n kọ́ túbú kékeré kan sí ọ̀gangan apá kejì ọjà náà tí wọ́n ti wọ́n ma ń tọ́júbẹrú sí di ọjọ́ ọjà ẹrú. Ọjọ́ márùn un márùn ún ni wọ́n nọ́jà ẹrú náà. Àwọn gèèbó yóò ma kò àwọn nkan bí dígí, àhàyá,ẹ̀tù [[ìbọn]] abọ́ ìjẹun, ọtí wisikí, àbùradà ati bẹ́ẹ̀ bẹ́ẹ̀ lọ.<ref>Cite web|date=2014-01-18|title=Badagry and the remaining marks of slave market|url=https://www.vanguardngr.com/2014/01/badagry-remaining-marks-slave-market/|access-date=2021-08-19|website=Vanguard News|language=en-US}}</ref>
Àmọ́ bí báyí, ọjà Velekete ti di àyè tí àwọn akẹ́kọ̀ọ́ àti àrìnrì-àjò ìgbafẹ́ ma ń wá bẹ̀ wò fún àwọn tí wọ́n bá fẹ́ mọ kúlẹ̀ kúlẹ̀ nípa bí òwò ẹrú ṣe gbóná tó ní àárín gbungbun ilẹ̀ Áfíríkà.
==Lára àwọn ibùdó tí ó ṣe pàtàkì nínú ìtàn òwò ẹrú náà ni_:==
 
* ìdílé Mo bee àti àwọn ohun ìtàn tí ó ń fi ìdílé náà hàn pẹ́lú ipa tí wọ́n kò nínú òwò ẹrú
* Ojú ọ̀nà ''Gbẹrẹfu'' náà jẹ́ ojú ọ̀ná kan tí ó lọ sí'' Point of No Return'' níbi tí àwọn ẹrú [[ọkùnrin]] àti [[obìnrin]], ọmọdékùnrin àti ọmọdébìnrin tí wọn tó 500,000 níye tí wọ́n ti kò lèrú mo ń gbà lọ wọkọ̀ ojú-omi lọ sí ìlú òyìnbó.
* Wọ́n ma ń fi tipá fún àwọn ẹrú ní omi inú [[kànga]] kan tí parí oògùn burúkú kan sí kí àwọn ẹrú ó má lè ba dojú ìjà kọ àwọn òyìnbó gẹ̀ẹ́sì tí wọ́n rà wọ́n, kí wọ́n má sì lè rántí ilé mọ́ láé.
*[[File:A portrait of negotiation process to the point of no return.jpg|thumb|Àwòrán ìdúná-dúrá lórí àwọn ẹrú tí wọ́n fẹ́ kó gba point of no return]]
Point of No Return ni ibi tí àwọn olówò-ẹrú ti ma ń dúná-dúrá ṣáájú kí wọ́n tó kò àwọn ẹrú wọkọ̀ ojú-omi.<ref>{{Cite web|date=2021-07-26|title=Badagry Slave Route: Slaves passed these 5 notable stops on their journey of no return|url=https://www.pulse.ng/lifestyle/food-travel/badagry-slave-route-slaves-passed-these-5-notable-stops-on-their-journey-of-no-return/mr1dbj4|access-date=2021-08-19|website=Pulse Nigeria|language=en}}</ref>
 
==Àwọn itọ́ka sí==
{{Reflist}}
 
{{DEFAULTSORT:Vlekete Slave Market}}
[[Category:16th-century establishments in Nigeria]]
[[Category:1502 establishments in Africa]]
[[Category:History of Lagos]]
[[Category:African slave trade]]
 
 
{{Lagos-stub}}
{{Retail-market-stub}}