Tina Mba jẹ́ òṣèré orí-ìtàgé ọmọ orílẹ̀-èdè Nàìjíríà tí wọ́n yàn fún àmì-ẹ̀yẹ òṣèrébìnrin tí ó tayọ níbi ayẹyẹ ẹlẹ́keèje ti Africa Movie Academy Awards

Tina Mba
Ọjọ́ìbí2 October[1]
Enugu State
Orílẹ̀-èdèNigeria
Iṣẹ́Actress
Àwọn ọmọ3

Iṣẹ́ ìṣe rẹ̀ àtúnṣe

Ní ọdún 2017, Tina kópa nínu àwọn eré bíi Isoken, Bariga Suger, Okafor's Law àti bẹ́ẹ̀bẹ́ẹ̀ lọ, tí ìwé ìròyìn pulse sì ṣe àpèjúwe rẹ̀ bíi “òṣèrébìnrin tí ó dára jù lọ́dún”. Níbi ayẹyẹ Africa Magic Viewers Choice Awards ti ọdún 2017, wọ́n yàán fún àmì-ẹ̀yẹ òṣèrébìnrin tí ó tayọ jùlọ nínu eré aláwàdà.[2] Ó ṣàlàyé wípé òun kò bá ti fẹ́ràn eré orí ìpele ju sinimá àgbéléwò lọ tóbá ṣe wípé owó rẹ̀ pọ̀ dáada. Ní ọdún 2016, ó kópa nínu eré afìfẹ́hàn kan tí àkọ́lé rẹ̀ jẹ́ Ufuoma, èyítí Ikechukwu Onyeka darí.[3] Ní Oṣù Kẹẹ̀wá ọdún 2017, ó tún kópa nínu eré Omoye, èyítí ó jẹ́ láti lòdì sí ìfipábánilòpọ̀.[4] Ní ọdún 2017 kan náà ló kópa nínu eré Isoken ní àjọṣepọ̀ pẹ̀lú Fúnkẹ́ Akíndélé àti Dakore Àkàndé. Ó kó ipa ìyá kan tó n fẹ́ kí ọmọ rẹ̀ obìnrin ṣe ìgbeyàwó ní kíákíá.[5]

Àṣàyàn àwọn eré rẹ̀ àtúnṣe

  • Isoken
  • Okafor's Law
  • Make a Move
  • Married but Living Single
  • Heroes and Zeroes
  • Tango with Me
  • The Tenant
  • Beneath Her Veil (2015)
  • Three Wise Men (2016)
  • Banana Island Ghost (2017)
  • The Bridge (2017 film)
  • Nigerian Prince (2018)
  • The Set Up (2019)

Ọ̀rọ̀ ayé rẹ̀ àtúnṣe

Ó jẹ́ ọmọ bíbí Ìpínlẹ̀ Ẹnúgu,[6] ó sì ti bí ọmọ méjì.[7]

Àwọn ìtọ́kasí àtúnṣe

  1. "CELEBRITY BIRTHDAY – TINA MBA". Yup Magazine. 2 October 2015. Archived from the original on 3 April 2018. Retrieved 11 November 2017. 
  2. "Tina Mba is unarguably the best Nollywood actress of 2017, so far". Pulse. 12 July 2017. Retrieved 11 November 2017. 
  3. Izuzu (30 August 2016). "Mike Ezuruonye, Peggy Ovire, Tina Mba star in new movie". Pulse. Retrieved 30 November 2017. 
  4. "Tina Mba, Stan Nze, others return in 'Omoye'". Vanguard. 21 October 2017. Retrieved 11 November 2017. 
  5. "Funke Akindele, Dakore Akande, Tina Mba, Joseph Benjamin star in new movie". Pulse. 18 August 2016. Retrieved 30 November 2017. 
  6. "I've been battered & broken------Tina Mba". Modern Ghana. 14 July 2009. Retrieved 12 November 2017. 
  7. Orenuga, Adenike (23 October 2014). "Marriage is a burden, don't go there" – Actress, Tina Mba". Dailypost Newspaper. Retrieved 11 November 2017.