Bella Awa Gassama jẹ́ òṣèrébìnrin ọmọ orílẹ̀-èdè Gámbíà.

Bella Awa Gassama
Orílẹ̀-èdèGambian
Orúkọ mírànAwa Gassama
Iṣẹ́Actress
Ìgbà iṣẹ́2004-present

Ìsẹ̀mí rẹ̀ àtúnṣe

Gassama ní ìbátan pẹ̀lú oníìdájọ́ bọ́ọ̀lù àfẹsẹ̀gbá tí n ṣe Bakary "Papa" Gassama.[1] Ó parí ẹ̀kọ́ girama rẹ̀ ní ilé-ìwé Marina International School ní ọdún 2004. Ó kó àkọ́kọ́ ipa rẹ̀ nínu fíìmù tí àkọ́lé rẹ̀ jẹ́ Arrou ní ọdún 2004 yìí kan náà. Wọ́n wo fíìmù náà níbi ayẹyẹ Pan-African Film Festival kan tí ó wáyé ní ìlú Los Angeles, Gassama náà sì tún rí yíyàn fún àmì-ẹ̀yẹ amúgbálẹ́gbẹ̀ẹ́ òṣèré tí ó dára jùlọ níbi ayẹyẹ 2nd Africa Movie Academy Awards.[2] Wọ́n tún yàán fún òṣèré ilẹ̀ Gámbíà tí ó dára jùlọ níbi ayẹyẹ Vinasha Film Festival.[3] Ní ọdún 2008 bákan náà, Gassama tún kó àkọ́kọ́ ipa rẹ̀ nínu fíìmù ilẹ̀ Nàìjíríà tí àkọ́lé rẹ̀ jẹ́ My Gambian Holiday pẹ̀lú àjọṣepọ̀ Desmond Elliot àti Oge Okoye.[4] Ó tún kó ipa amúgbálẹ́gbẹ̀ẹ́ nínu fíìmù Mirror Boy ti ọdún 2011, ní àjọṣepọ̀ pẹ̀lú Fatima Jabbe àti Genevieve Nnaji.[5] Ní ọdún 2012, Gassama parí ìkẹ́kọ̀ọ́ láti ilé-ẹ̀kọ́ gígaTask Crown College.[6]

Gassama kópa nínu eré Sidy Diallo kan ti ọdún 2014 tí àkọ́lé rẹ̀ jẹ́ The Soul.[7] Wọ́n yàán fún àmì-ẹ̀yẹ amúgbálẹ́gbẹ̀ẹ́ òṣèré tí ó dára jùlọ níbi ayẹyẹ Zulu African Film Academy Awards.[8] Ó kópa nínu eré tẹlifíṣọ̀nù ti ọdún 2019 kan tí àkọ́lé rẹ̀ jẹ́ Nakala.[9] Ní Oṣù kọkànlá Ọdún 2019, Gassama ṣe ìgbéyàwó pẹ̀lú Pa Lie Low.[10]

Àwọn àṣàyàn eré rẹ̀ àtúnṣe

  • 2004: Arrou (Idena)
  • 2008: Isinmi Gambian mi
  • 2011: Ọmọkunrin Digi
  • 2013: Idanimọ ti ko tọ
  • 2014: Ọkàn
  • 2019: Nakala (jara TV)

Àwọn ìtọ́kasí àtúnṣe

  1. Gassama, Awa (9 January 2014). "Gambia: Papa Gassama - It Takes Hard Work, Dedication to Get to the Top". https://allafrica.com/stories/201401091185.html. Retrieved 16 October 2020. 
  2. "Introducing (Bella Awa Gassama)". The Standard. 5 May 2014. https://standard.gm/introducing-bella-awa-gassama/. Retrieved 16 October 2020. 
  3. Khan, Alieu (28 November 2006). "Who is your Gambian actor and actress of the year?". Africa.gm. Archived from the original on 18 November 2021. Retrieved 16 October 2020. 
  4. "Introducing (Bella Awa Gassama)". The Standard. 5 May 2014. https://standard.gm/introducing-bella-awa-gassama/. Retrieved 16 October 2020. 
  5. Wally, Omar (6 June 2011). "Gambia: 'The Mirror Boy' Launched in Gambia". https://allafrica.com/stories/201106062042.html. Retrieved 16 October 2020. 
  6. "Introducing (Bella Awa Gassama)". 5 May 2014. https://standard.gm/introducing-bella-awa-gassama/. Retrieved 16 October 2020. 
  7. Obi, Ikenna. "THE SOUL premiers: 26th of April 2014 at the LightHouse in Camberwell.". FabAfriq. Retrieved 16 October 2020. 
  8. "ZAFFA Unveils 2014 Nominees". Pulse. 25 August 2014. Retrieved 16 October 2020. 
  9. "Come and get it! Bella Gassama shows some leg in promo photo". What's On Gambia. 30 November 2019. Archived from the original on 17 October 2020. Retrieved 16 October 2020. 
  10. "Congratulations! Nollywood Actress Bella Gassama gets married to US-based Pa Lie Low". What's On Gambia. 30 November 2019. Archived from the original on 20 October 2020. Retrieved 16 October 2020. 

Àwọn ìtakùn Ìjásóde àtúnṣe