Olóyè Kofoworola Abeni Pratt Hon. FRCN (1910–1992) jẹ́ olùtọ́jú  aláìsàn tí wọ́n bí sí orílẹ̀ èdè Nàìjíríà tí ó jẹ́ olùtọ́jú aláìsàn dúdú tí ó kọ́kọ́ ṣiṣẹ́ pẹ̀lú National Health Service.[1] Ó sì jẹ igbákejì ààrẹ ti International Council of Nurses àti ènìyàn dúdú àkọ́kọ́ tí ó má a jẹ́ Chief Nursing Officer fún Nàìjíríà, tí ó ṣiṣẹ́ pẹ̀lú  Federal Ministry of Health.[2][3]

Olóyè
Kofoworola Abeni Pratt
Hon. FRCN
Ọjọ́ìbí1910
Nàìjíríà
AláìsíỌjọ́ kejìdínlógún Oṣù kẹfà ọdún 1992
Orílẹ̀-èdèỌmọ orílẹ̀ èdè Nàìjióríà
Iṣẹ́Olùtọ́jú aláìsàn

Wọ́n bí Pratt is ẹbí olókìkí kan ní Nàìjíríà, ó kàwé láti dí olùkọ́ ní United Missionary College ní Ibadan, lẹ́yìn tí bàbà rẹ̀ kò fi taratara fọwọ́sí pé kí ó ṣe iṣẹ́ ìtọ́jú aláìsàn.[4] Lati 1936 sí 1940 ó jẹ́ olùkọ́ ní Church Missionary Society girls' school ní Nàìjíríà.[4]

O fẹ́ òyìnbó, Dr. E. S. O. Pratt,[4] lẹ́yìn tí ó kọjá sí England ní ọdún 1946,[4] ó kọ́ ẹ̀kọ́ nípa ìtọ́jú aláìsàn ní Nightingale School tí ó wà ní St Thomas' Hospital, ní London,[1][3] ó sì yege gẹ́gẹ́ bí  State Registered Nurse ní ọdún  1950.[4] Kò wọ́pọ̀ kí wọ́n gba ẹni tí ó ti lọ́kọ lati ṣisẹ́ ìtọ́jú aláìsàn ní àkókò yẹn.[3]

Ní àkókò rẹ̀ ní London, ó jáfáfá ní ẹgbẹ́  West African Students' Union,[4] ẹgbẹ́ àwọn akẹ́kọ́ lati àwọn orílẹ̀ èdè tó wà ní ìwọ oòrùn Afíríkà tí wọ́n ń kàwé ní United Kingdom, tí ó sì jẹ́ pé ní ọdún 1942, wọ́n jà fitafita fún òmìnira àwọn ìletò ìwọ oòrùn Gẹ̀ẹ́sì.[5]

Pratt padà sí orílẹ̀ èdè Nàìjíríà ní ọdún 1954.  Wọ́n yàn-án ní ògá àwọn olùtọ́jú aláìsàn lóbìrin ní University College Hospital ní Ibadan nínú ọdún mẹ́ẹ̀wá, tí ó jẹ́ pé òhun ní ọmọ orílẹ̀ èdè Nàìjíríà àkọ́kọ́ tí ó má a di ipò yìí mú.[4] Ó jẹ́ alábójútó fún ètò ìléra ti ìlú èkó ní bí ọdún 1970.[6]

Ní ọdún  1973 ó gba ẹ̀bùn  Florence Nightingale Medal lati ọwọ́ International Committee of the Red Cross.[7]

Ààrẹ  Nigerian Red Cross Society, Sir Adetokunbo Ademola, ní ó fun ní ẹ̀bùn yìí ní ọjọ́ ọkànlélógún oṣù kejìlá ọdún1973.[8]

Ní ọdún 1979 wọ́n sọọ́ dí ọmọ ẹgbẹ́ Royal College of Nursing; èyí tí wọ́n fi dáa lọ́la[9]

Ó kú ní ọjọ́ kejìdínlógún Oṣù kẹfà ọdún 1992.[10]

Àwọn ìtọ́kasí àtúnṣe

  1. 1.0 1.1 "Wonderful adventures: How did Mary Seacole come to be viewed as a pioneer of modern nursing?". Times Literary Supplement: p. 14-15. 6 December 2013. Archived from the original on 4 April 2016. https://web.archive.org/web/20160404064726/http://www.uoguelph.ca/~cwfn/short/tls-seacole.htm. Retrieved 11 July 2016. 
  2. Bell, L. M. (October 1967). "Kofoworola Abeni Pratt; third vice-president, International Council of Nurses". Int Nurs Rev. 14 (5): 7–10. PMID 4864502. 
  3. 3.0 3.1 3.2 "Listener Week".
  4. 4.0 4.1 4.2 4.3 4.4 4.5 4.6 Matera, Marc (May 2008). Black Internationalism and African and Caribbean Intellectuals in London 1919–1950. doi:10.7282/T38S4Q7V. https://rucore.libraries.rutgers.edu/rutgers-lib/24439/. Retrieved 11 July 2016. 
  5. Hakim Adi, West Africans in Britain 1900–1960: Nationalism, Pan-Africanism and Communism, London: Lawrence & Wishart, 1998.
  6. "Kofoworola Abeni Pratt".
  7. "Twenty-fourth award of the Florence Nightingale Medal". International Review of the Red Cross (146): 242. May 1973. https://www.loc.gov/rr/frd/Military_Law/pdf/RC_May-1973.pdf. Retrieved 11 July 2016. 
  8. "Twenty-fourth award of the Florence Nightingale Medal". International Review of the Red Cross (147): 250. May 1974. https://www.loc.gov/rr/frd/Military_Law/pdf/RC_May-1974.pdf. Retrieved 11 July 2016. 
  9. "RCN Fellowship and Honorary Fellowship Roll of Honour"[Ìjápọ̀ tí kò ṣiṣẹ́ mọ́] (PDF).
  10. "In the estate of Kofoworola Abeni Pratt deceased". The Times: p. 16. 24 April 1993. http://find.galegroup.com/ttda/newspaperRetrieve.do?sgHitCountType=None&sort=DateAscend&tabID=T003&prodId=TTDA&resultListType=RESULT_LIST&searchId=R1&searchType=BasicSearchForm&currentPosition=1&qrySerId=Locale%28en%2C%2C%29%3AFQE%3D%28tx%2CNone%2C22%29Kofoworola+Abeni+Pratt%24&retrieveFormat=MULTIPAGE_DOCUMENT&userGroupName=lancs&inPS=true&contentSet=LTO&&docId=&docLevel=FASCIMILE&workId=&relevancePageBatch=IF501975871&contentSet=TDA&callistoContentSet=TDA&docPage=article&hilite=y. Retrieved 11 July 2016.