Lateef Adegbite. (Ọjọ́ ìbí, ogúnjọ́ oṣù kẹta ọdún 1933. O si di oloogbe ni ọjọ kejìdínlọ́gbọ̀n oṣù kẹsan ọdun 2012). Nígbà ayé rẹ, ó jẹ́ agbejọ́rò kan tí ó di Attorney gbogboogbo (Attorney General) ti apá ìwọ̀ oorun ilẹ̀ Nàìjíríà Western Region of Nigeria ki o to wa di akọ̀wé gbogboogbo ti ìgbìmọ̀ gíga fún àmójútó ọ̀rọ̀ Islam ní Nàìjíríà.[2]

Lateef Adegbite
Ọjọ́ìbí20 Oṣù Kẹta 1933 (1933-03-20) (ọmọ ọdún 91)
Aláìsí28 September 2012[1]
Orílẹ̀-èdèNigerian

Ìbí àti ètò-ẹ̀kọ́ àtúnṣe

Abdul-Lateef Oladimeji Adegbitẹ ni a bi ni Ogúnjọ́ oṣù kẹta ọdún 1933 sínú ẹbí Mùsùlùmí Ẹ̀gbá ti o múná ní ìlú Abẹ́òkúta, Ìpínlẹ̀ Ògùn. Gẹ́gẹ́ bí àkọsílẹ̀ kan, Ó lọ sí ilé-ìwé Methodist Abeokuta sùgbọ́n Ó sọ fúnrararẹ̀ pé Ò ún kọ́kọ́ lọ sí ilé-ẹ̀kọ́ Arabiki lẹhinna ni O un wọ ilé-ẹ̀kọ́ alakọbẹrẹ ti Paulu Mímọ́ (St Paul) ní Ìgbórè, Abẹ́òkúta ní ọdún 1942. Nígbàtí Adegbitẹ di ọmọ ọdún mẹsan ní Ó gba ìwè-ẹ̀kọ́ sikolashipu láti lọ sí ilé-ìwé gíga ti Ọba (King's College) ní Èkó níbití O ti jẹ́ ọ̀kanlára àjọ olùdásílẹ̀ àti àarẹ orílẹ̀ àkọ́kọ́ fún àwùjọ akọ́ ẹ̀kọ́ mùsùlùmí ti orílẹ̀ èdè Naijiria Muslim Students Society of Nigeria. Ó parí ilé-ẹ̀kọ́ ní ọdún 1956.

Ní ọdún 1959, asájú ẹkún ti ìwọ̀ oorun ni Nàìjíríà, Oloye Obafẹmi Awolowọ fún Adegbitẹ ni sikolashipu kan láti rin ìrìn-àjò lọ sí ìlú gẹ̀ẹ́sì lat́i lọ kọ́ ẹ̀kọ́ gboyè nípa òfin lábẹ́ èrò tí olóyè F.R.A Williams là kalẹ̀. Adegbitẹ lọ sí Yunifásítì ti Southhampton, Ó sì kàwé gboyè lórí ìmọ̀ òfin ní oṣù keje ọdún 1962. Lẹhinna, Ó kàwé ní ilé-ìwé gíga ti òfin fún àwọn asojú, Lancaster Gate ní ìlú London àti lẹhinna ni Grey's inn (1963-1965) Ó tún gba sikolashipu ti Commonwealth fún ìkẹ́kọ̀ gboyè oní pele kejì ní ilẹ̀ gẹ̀ẹ́sì. Ó bẹ̀rẹ̀ iṣẹ́ olùkọ́ ìmọ̀ òfin ní Yunifásítì ìlú èkó tí Ó sì di ipò yí mú títí tí O fi lọ́ da iṣẹ́ àdáni tirẹ̀ sílẹ̀ nínú oṣù kẹsan ọdún 1976.

Iṣẹ́ àtúnṣe

Ní ọdún 1971 wọ́n yan Adegbitẹ gẹ́gẹ́ bi koomisoanna fún ìjọba agbègbè àti ti ọ̀rọ̀ oyè ní ẹkùn ìwọ oorun ti Naijiria lakoko ìjọba ológun ti ọ̀gágun Christopher Oluwọle Rotimi. Lehinna, wọ́n tún yan an gẹ́gẹ́ bi koomisoanna fún ìdájọ́ àti Attorney-Gbogboogbo tí ẹkùn ìwọ̀ oorun ní ọdún 1973. Ní oṣù kẹwà ọdún 1976, Ó ṣe ìdásílẹ̀ àjọ ilé-iṣẹ́ òfin ti Lateef Adegbitẹ tí Ò un fúnrarẹ̀ si jẹ olórí alájọṣepọ̀ èyí tí ọ́fíìsì àkọ́kọ́ wọn wa ní Èkó àti ẹ̀ka kan ní Abẹ́òkúta. Òfin òwò àti àjọ (Commercial and Corporate Law ) ní o jẹ́ pàtàkì iṣẹ́ wọn. Ẹ̀ka ófíìsì ti Abẹ́òkúta wa ni Àgọ́-Ọ̀bà. Adegbitẹ jẹ́ ọ̀kan lára àwọn tí wọ́n dá ẹgbẹ́ amuludun ti Abẹ́òkúta sílẹ̀ ní ọdún 1972.[3]

Adegbitẹ jẹ́ ààrẹ ìgbìmọ̀ ti Olympic ti ilẹ̀ Naijiria Nigeria Olympic Committee láti ọdún 1972 sí ọdún 1985. Ó jẹ́ olórí-asíwájú àti alága ti ìgbìmọ̀ ìṣàkóso Yunifásítì ilu Maiduguri láti ọdún 1984 sí ọdún 1990. Ó di ọmọ ẹgbẹ́ ìgbìmọ̀ aláṣẹ ìgbìmọ̀ okoowo ti ìpínlẹ̀ Èkó. Lehinna Ó di ọ̀gá àgbà ti iṣẹ́ àti ìṣèdúró. Wọ́n fi oyè alakoso tí ó ga jùlọ ní ilẹ̀ Naijiria (Commander of the order of the Niger (CON)) dá Adegbitẹ lọ́lá. Ó tún jẹ àwọn oyè ìbílẹ̀ bi i séríkí ti ilẹ̀ Ẹ̀gbá àti Bàbá Àdínì ti Musulumi Ẹ̀gbá. Ní ọjọ́ kẹsan oṣù kẹta ọdún 2011, Aarẹ Goodluck Jonathan yan an gẹ́gẹ́ bi alága ìgbìmọ̀ lórí àkọsílẹ̀ ìmọ̀ lórí aàbò àti ojuṣe abẹ́lé (Chairman, Presidential Committee on Public Awareness on Security and Civic Responsibilities) .[4]

Dọ́kítà Lateef Adegbitẹ jẹ́ arákùnrin si olóògbé olókìkí àti ògbóǹtarìgì akọìtàn ọ̀jọ̀gbọ́n Saburi Biobaku (1918-2001), ẹni tí o tí jẹ gíwá Yunifásítì ti Èkó tẹ́lẹ̀.

Olórí Mùsùlùmí àtúnṣe

Ní ìjọ constituent ní ọdún1976, Adegbitẹ jiyàn nípasẹ̀ ojúrere pé ki wọ́n ṣe agbékalẹ̀ ilé ẹjọ́ àpètúnpè tí Islam sí àwọn Ìpínlẹ̀ tí ó wà ní guusu ilẹ̀ Naijiria. Ó sọ wípé àwọn Musulumi ní ètò láti pe ki a ṣe ìdájọ́ won ní ìbámu sí òfin Sharia. O se e ní àlàyé pé "Àwọn Musulumi kò ní òfin àti ìlànà òmíràn yàtọ̀ sí èyí tí Sharia ti gbé kalẹ̀. Sharia gẹ́gẹ́ bí òfin mímọ́ yọrí ju gbogbo òfin ìlú àti ti ìhùwàsí lọ."Adegbitẹ fẹ́ ṣe àtìlẹ́hìn fún akitiyan M.K.O. Abiọla láti ṣe agbékalẹ̀ Sharia sí àwọn ìpínlẹ̀ guusu ní ìbẹ̀rẹ̀ àwọn ọdún 1990.[5] Ó tún fi ipò yíí múlẹ̀ ní oṣù kejìlá ọdún 2002 ní àkókò aríyànjiyàn tí ó gbooro ní àárín àwọn kristiani àti àwọn musulumi. Adegbitẹ jẹ́ alága ìgbìmọ̀ àwọn arìnrìn ajo mímọ́ ní Ìpínlẹ̀ Ògùn ati ọmọ ẹgbẹ́ ìgbìmọ̀ àwọn arìnrìn ajo ti orílẹ̀. Nígbàtí Ibrahim Dasuki di Sultan ti Sokoto ní ọdún 1988 àti Aare-Gbogboogbo fún ìgbìmọ̀ gíga ti Naijiria fún ọ̀rọ̀ Islam ni Naijiria (NSCIA), Adegbitẹ ni wọ́n yàn gẹ́gẹ́ bi Akọ̀wé-Gbogboogbo fún ìgbìmọ̀ naa. Lábẹ́ àkóso Adegbitẹ àti Dasuki ni NSCIA, èyí tí wọ́n fi ìdí rẹ múlẹ̀ ní ọdún 1974, di èyí tí o tun bo n ṣe iṣẹ́ pẹ̀lú ìtara.

Ní ìparí ọdún 2002 àti ìbẹ̀rẹ̀ ọdún 2003, Adegbitẹ ṣe àríyànjiyàn ti gbogbo ènìyàn pẹ̀lú onkowe gba ẹ̀bùn Nobel, Wọle Ṣoyinka, ẹni tí ó fi ẹ̀sùn kan àwọn olùdarí musulumi pe wọ́n ru ìwà-ipá sókè lẹ́hìn rúdurùdu tí ó ṣẹlẹ̀ ní ìlu Kàdúná ti o mu ki ọ̀pọ̀lọpọ̀ ẹ̀mí ṣòfò. Ìbẹ̀rẹ̀ ọ̀tẹ̀ yí ni àtakò ti o wáyé láti ọ̀dọ̀ àwọn Musulumi pe ki wọ̀n ṣe ìdádúró ìdíje Arẹwà Ọ̀dọ́bìnrin Àgbáyé (Miss World) ní Naijiria. Rògbòdìyàn yi tún bọ̀ gbèrú si nítorí o un tí àwọn musulumi kà sí gẹ́gẹ́ bi gbólóhùn òdì ni ìròyìn tì oníròyìn, Isioma Daniel kọ sínú ìwé ìròyìn ti kristiani kan pe ti o ba jẹ wípé Woli bá lọ sí ibi ìṣẹ̀lẹ̀ arẹwà Ọ̀dọ́bìnrin Àgbáyé yi ni, kò bá ti mú ọ̀kan nínú àwọn olùdíje yi fi ṣe ìyàwó. Lehinna ni wọ́n sọ wípé igbákejì gómìnà ti Ìpínlẹ̀ Zamfara, Mamauda Aliyu Shinkafi sọ ọ̀rọ̀ gbangba pé ó lè jẹ́ òfin fún Musulumi láti ta ẹ̀jẹ Isioma Daniel sílẹ̀. Lẹ́sẹ̀kẹsẹ̀ ni Adegbitẹ ti lòdì sí ọ̀rọ̀ yí. Ó ní níwọ̀n ìgbàtí akọìròyìn yí kii ṣe Musulumi àti wípé ìwé ìròyìn yí ti tọrọ gáfárà ní gbangba.[6]

Adegbitẹ sọ nínú ìwé ìròyìn ti oṣù kẹwa ọdún 2003 pé tí wọ́n ba le yi ilẹ̀ Amẹ́ríkà àti àwọn alájọṣepọ̀ rẹ lọ́kàn padà láti gbà pé gbogbo ìpayà tí o nmulẹ kákàkiri àgbáyé yí ò dínkù tí ìdájọ́ òdodo bá lè fi ẹsẹ̀ múlẹ̀ ní àárín ìla-oorun. Ẹ fún àwọn ará Palestini ní ilẹ̀ wọn padà, ko si ni si àyè fún Osama Bin Ladens tí ayé yi láti gbérí. Láì sí ìdajọ òdodo, ko le si alaafia. Nígbàtí UNESCO ṣe ètò àpérò lórí ọ̀rọ̀ àwọn ẹ̀sìn ní Àbújá ní oṣù kejìlá ọdún 2003, wọ́n pe Adégbìtẹ́ láti sọ̀rọ̀ lórí ipa tí àwọn olùdarí ẹ̀sìn ńkó láti dẹ́kun rògbòdìyàn.

Ikú rẹ̀ àtúnṣe

Dọ́kítà Adegbitẹ kú sí ìlú Èkó ní ọjọ́ kejìdínlọ́gbọ̀n, oṣù kẹsan ọdún 2012.[7]

Àwọn ìtọ́kasí àtúnṣe

  1. Adebowale, Yemi (20 March 1933). "Nigeria: Foremost Islamic Scholar Lateef Adegbite Dies at 79". allAfrica.com. Retrieved 29 September 2012. 
  2. ADEFAKA, Bashir (2010-01-29). "The position of Islam on terrorism - Lateef Adegbite". Vanguard News. Retrieved 2020-02-07. 
  3. "History – Abeokuta Club". Abeokuta Club – Ire o! Baa wa!!. Archived from the original on 2020-02-07. Retrieved 2020-02-07. 
  4. "Jonathan sets up Presidential Committee on Security Awareness, with Alhaji Lateef Adegbite as Chairman". Safer Nigeria Resources. 2011-03-11. Retrieved 2020-02-07. 
  5. "Violence in Nigeria". Google Books. Retrieved 2020-02-11. 
  6. "Islamic Criminal Law in Northern Nigeria". Google Books. Retrieved 2020-02-11. 
  7. "BREAKING NEWS: Islamic leader, Lateef Adegbite, dies at 79". Premium Times Nigeria. 2012-09-28. Retrieved 2020-02-07.