Elizabeth Ọmọ́wùnmí Tekovi Da-Silva (tí a bí ní Oṣù Kẹẹ̀fà Ọjọ́ 10, Ọdún 1978) jẹ́ òṣèré ọmọ orílẹ̀-èdè Nàìjíríà àti Tógò tí ó maá n sábà kópa ní ọ̀pọ̀lọpọ̀ ìgbà nínu fíìmù Yorùbá ti Nàìjíríà. Ní ọdún 2016, wọ́n yan Da-Silva fún àmì ẹ̀yẹ City People Movie Award fún ti òṣèré amúgbálẹ́gbẹ̀ẹ́ tó dára jùlọ (ẹ̀ka ti eré Yorùbá) níbi ayẹyẹ City People Entertainment Awards.[1] Ní ọdún 2018 bákan náà, ó gba àmì ẹ̀yẹ fún òṣèré amúgbálẹ́gbẹ̀ẹ́ tó dára jùlọ níbi ayẹyẹ Best of Nollywood Awards.[2]

Liz Da-Silva
Ọjọ́ìbíElizabeth Omowunmi Tekovi Da-Silva
10 Oṣù Kàrún 1978 (1978-05-10) (ọmọ ọdún 45)
Obalende, Ipinlẹ Eko
Orílẹ̀-èdèTogo ati Naijiria
Iṣẹ́Osere
Ìgbà iṣẹ́2004–Iwoyi
Àwọn ọmọ1

Ìbẹ̀rẹ̀pẹ̀pẹ̀ ayé àti ẹ̀kọ́ rẹ̀ àtúnṣe

A bí Da-Silva sí ọwọ́ àwọn òbí tí n ṣe ará Tógò ṣùgbọ́n tí wọ́n n gbé ní Nàìjíríà. A bi ní agbègbè tí a mọ̀ sí Obálendé ní Ìpínlẹ̀ Èkó níbití àwọn òbi rẹ̀ gbé, níbẹ̀ ló sì ti lo ìgbà èwe rẹ̀. Nínu ìfọ̀rọ̀wánilẹ́nuwò kan pẹ̀lú àwọn oniròyìn kan lórílẹ̀-èdè Nàìjíríà, ó ṣàlàyé pé Ìlú Èkó dà gẹ́gẹ́ bi ilé òun, ó sì sọ nínu ìfọ̀rọ̀wánilẹ́nuwò náà pé òún wá láti ilé olórogún.[3] Da-Silva lọ sí Ireti Grammar School fún ètò-ẹ̀kọ́ ìwé mẹ̀wá rẹ̀, ó sì tẹ̀síwájú lọ sí Ilé-ẹ̀kọ́ gíga ti Ìpínlẹ̀ Èkó níbi tó ti gba oyè-ẹ̀kọ́ B.Sc.[1][4]

Iṣẹ́ ìṣe rẹ̀ àtúnṣe

Nínu ìfọ̀rọ̀wánilẹ́nuwò kan Da-Silva ṣàlàyé pé òún bẹ̀rẹ̀ sí nìfẹ́ sí láti darapọ̀ mọ́ ilé-iṣẹ́ fíìmù ti Yorùbá ti Nàìjíríà ní àkókò tí òún wà ní ilé-ìwe girama. Nígbà náà lòwún bẹ̀rẹ̀ sí kópa nínu àwọn eré ti ilé-ìwé. Da-Silva nínu ìfọ̀rọ̀wánilẹ́nuwò kan pẹ̀lú àwọn oniròyìn The Punch ṣàlàyé pé òún kó ipa àkọ́kọ́ ní ilé-iṣẹ́ fíìmù Yorùbá ti Nàìjíríà ní ọdún 2004 nípasẹ̀ ìrànlọ́wọ́ Ìyábọ̀ Òjó.[5] Da-Silva di gbajúmọ̀ òṣèrè lẹ́hìn tí ó kó àwọn ipa gbòógì nínu fíìmù méj̀i kan; àkọ́lé àkọ́kọ́ ni Wákàtí Méta látọwọ́ Wale Lawal àti fíìmù kan ta pe àkọ́lé rẹ̀ ní Omidan látọwọ́ Ìyáboọ̀ Òjó.[6][3]

Da-Silva ní ọdún 2012 ṣe àkọ́kọ́ ìgbéréjáde rẹ̀ pẹ̀lu fíìmù tí àkọ́lé rẹ̀ jẹ́ Mama Insurance, èyítí ó ṣe ìfihàn Ayò Mógàjí, Lánre Hassan,Ìyábọ̀ Òjó, Rónkẹ́ Òjó, àti Doris Simeon .[7][8]

Ìgbé ayé rẹ̀ àtúnṣe

Da-Silva jẹ́ ọmọ orílẹ̀-èdè Nàìjíríà nípasẹ̀ bíbí àti ọmọ orílẹ̀-èdè Tógò nípasẹ̀ àwọn òbi rẹ̀. Da-Silva ti ṣàlàyé Ìpínlẹ̀ Èkó bí ilé rẹ̀, ṣùgbọ́n ó sì ní àdìsọ́kàn láti ní ìṣepọ̀ pẹ̀lú àwọn mọ̀lẹ́bí rẹ̀ ní Tógò. Da-Silva Ní ọdún 2013 yípadà láti Krìstẹ́nìIslam.[8][9][10]

Àwọn Àmì-ẹ̀yẹ Àti Yíyàn Rẹ̀ àtúnṣe

Year Award Category Result Ref
2018 City People Entertainment Awards Best Supporting Actress of the Year (Yoruba) Wọ́n pèé
Best of Nollywood Awards Best Supporting Actress –Yoruba Gbàá

[11]

Ipa àtúnṣe

Da-Silva lórúkọ, Bukky Wright gẹ́gẹ́ bí àwòkọ́ṣe rẹ̀ nínú ilé iṣẹ́ fíìmù Yorùbá ní Nàìjíríà ó sì sọ pé òun ti nípa lórí, ọ̀nà ìṣèré rẹ̀ ní pàtàkì. [12]

Àwọn Fíìmù Rẹ̀ Tí A Yàn àtúnṣe

  • Ore l’ore Nwoto (2007)
  • Omidan
  • Desire
  • Itanje
  • Mama Insurance
  • Alebu kan
  • Mawo’badan
  • Tasere
  • Mama insurance

Àwọn ìtọ́kasí àtúnṣe

  1. 1.0 1.1 Kehinde, Seye (2018-09-10). "Top Actress, LIZ DA SILVA Goes Into Fashion •Calls Her Label TEKOVI D'TAILOR". City People Magazine (in Èdè Gẹ̀ẹ́sì). Retrieved 2019-12-18. 
  2. "BON Awards 2018: Mercy Aigbe, Tana Adelana shine at 10th edition". Pulse Nigeria (in Èdè Gẹ̀ẹ́sì). 2018-12-09. Retrieved 2019-12-18. 
  3. 3.0 3.1 Published. "Actors should have a back-up plan — Liz Da Silva". Punch Newspapers (in Èdè Gẹ̀ẹ́sì). Retrieved 2019-12-18. 
  4. "Liz Da Silva: 13 things you must know about the sexy Nollywood actress". Nigerian Entertainment Today (in Èdè Gẹ̀ẹ́sì). 2015-12-06. Retrieved 2019-12-19. 
  5. Nigeria, Information (2018-03-23). ""Why I’m still single"- Actress, Liz Da-Silva". Information Nigeria (in Èdè Gẹ̀ẹ́sì). Retrieved 2019-12-19. 
  6. Nigeria, Information (2018-04-18). ""The Secret Things I Did To Remain Relevant In Nollywood"-Popular Yoruba Actress, Liz da Silva Explodes". Information Nigeria (in Èdè Gẹ̀ẹ́sì). Retrieved 2019-12-19. 
  7. "Marriage failures begin on newspaper pages—Liz Da Silva". Vanguard News (in Èdè Gẹ̀ẹ́sì). 2018-06-09. Retrieved 2019-12-19. 
  8. 8.0 8.1 Àṣìṣe ìtọ́kasí: Invalid <ref> tag; no text was provided for refs named :22"
  9. Legit.ng (2013-07-04). "Actress, Liz Da Silva Converts To Islam Because Of Baby". Legit.ng - Nigeria news. (in Èdè Gẹ̀ẹ́sì). Retrieved 2019-12-19. 
  10. "Liz Da Silva converts to Islam". The Eagle Online (in Èdè Gẹ̀ẹ́sì). 2013-07-06. Retrieved 2019-12-19. 
  11. "BON Awards | Nominees for the Best of Nollywood Awards, 2018" (in Èdè Gẹ̀ẹ́sì). Archived from the original on 19 December 2019. Retrieved 19 December 2019. 
  12. "Liz Da Silva: 13 things you must know about the sexy Nollywood actress". Nigerian Entertainment Today (in Èdè Gẹ̀ẹ́sì). 6 December 2015. Retrieved 19 December 2019.