Olusegun Agagu

Olóṣèlú

Olusegun Kokumo Agagu (born 16 February 1948) je oloselu omo ile Naijiria ati Gomina Ipinle Ondo lati 29 May, 2003 titi di 23 February, 2009 nigbati Ile-ejo Alatunejoda ni Ilu Benin fagile idiboyan April 2007 nitori pe ko bo fin mu.

Olusegun Agagu
Gómìnà Ipínlẹ̀ Òndó 15un
In office
May 29, 2003 – February 23, 2009[1]
Arọ́pòOlusegun Mimiko
Àwọn àlàyé onítòhún
Ọjọ́ìbíOṣù Kejì 16, 1948 (1948-02-16) (ọmọ ọdún 76)
Okiti-Pupa, Ipinle Ondo, Nigeria
Ẹgbẹ́ olóṣèlúPeople's Democratic Party
(Àwọn) olólùfẹ́Olufunke Agagu.

Wọ́n bí i ní ferbruary 16, 1948 ní Òkìtìpupa; Ondo State. Ó bẹ̀rẹ̀ ilé-ẹ̀kọ́ ní St Luké’s Anglican School, Òkìtì pupa ní 1954. Ó tún lọ sí Ebenezer Methodist School, Òkè-Àdó, Ìbàdàn ní 1958. Ó tún lọ sí Baptist Primacy School, Sabon-gari, Kano. Ó wá parí ẹ̀kọ́ primary School rẹ̀ ní Ebenezer African Church School, Ibadan. Lẹ́yìn èyí, ó lọ sí ìbàdàn Grammar School ní 1961. Lẹ́yìn èyí, ó lọ sí University Ìbàdàn láti ka Botany. Torí pé ó mọ Geology dáadáa, wọ́n fún un ní ẹ̀kọ́-ọ̀fẹ́ Gulf oil láti ka Geology lẹ́yìn ọdún kìíní. Lẹ́yìn ẹ̀kọ́ rẹ̀ ní University, ó bá Guif oil ṣiṣẹ́ fún ọdún méjì kí ó tó wá gbṣẹ́ sí University of Ìbàdàn gẹ́gẹ́ bí Assistant Lecturer ní 1972. ó lọ kàwé fún oye master rẹ̀ ní University of Texas láàrin 1973 sí 1974. Ó gbá PhD ní Petroleum Geology ní ní University of Ìbàdàn ní 1978. Ní 1988. ó fi UI sílẹ̀, ó sì bẹ̀rẹ̀ síi ṣe òṣèlu. Kò pé lẹ́yìn èyí, ó di igbákejì Gómínà ìpínlẹ̀ Oǹdó. O sì ti bẹ̀rẹ̀ sí í ṣe gómìnà ìpínlẹ̀ Oǹdó láti 2003 títí di ìgbà tí a ń kòwé yòí ní 2008.




Itokasi àtúnṣe