Iyabo Obasanjo-Bello

Olóṣèlú Nàìjíríà

Iyabo Obasanjo-Bello (ọjọ́-ìbí: ọjọ́ kẹ́ta-dín-lọ́gbọ̀n oṣù kẹrin, ọdún 1967) jẹ́ ọmọ ilé ìgbìmọ̀ aṣòfin èyí tí a sì lè pè ní "sẹ́nétọ̀" Nàìjíríà tẹ́lẹ̀ àti ọmọbìnrin Ààrẹ orílẹ̀-èdè Nàìjíríà nígbà kan rí, Olusegun Obasanjo àti ìyàwó rẹ̀ Oluremi Obasanjo. [1][2]

Iyabo Obasanjo
Senator for Ogun Central
In office
5 June 2007 – 6 June 2011
AsíwájúIbikunle Amosun
Arọ́pòOlugbenga Onaolapo Obadara
Àwọn àlàyé onítòhún
Ọjọ́ìbí27 Oṣù Kẹrin 1967 (1967-04-27) (ọmọ ọdún 56)
Lagos, Nigeria
Ọmọorílẹ̀-èdèNigerian
Ẹgbẹ́ olóṣèlúPeoples Democratic Party
(Àwọn) olólùfẹ́
Oluwafolajimi Akeem Bello
(m. 1999; div. 2003)
Àwọn ọmọ1
Àwọn òbí
ResidenceUnited States
Alma mater
Profession
  • Politician
  • veterinarian
  • epidemiologist

Ìbẹ̀rẹ̀pẹ̀pẹ̀ Ayé Rẹ̀ Àti Ẹ̀kọ́ àtúnṣe

Obasanjo lọ sí ilé-ìwé Corona ní Victoria Island, Èkó, Capital School ní Kaduna, àti Queen's College ní Èkó. Ó gba òye nípa Òògùn ti ogbó ti Ilé-ìwé gíga Yunifásítì ìlú Ibadan ní ọdún 1988, òye titun ní ẹ̀kọ́ nípa àjàkálẹ̀-àrùn láti University of California, Davis ní Davis, California, United States, ní ọdún 1990, àti òye ńlá, PhD ní ẹ̀kọ́ kan náà láti Cornell University ní Ithaca. New York, ní ọdún 1994. [3]

Ayé Rẹ̀ àtúnṣe

Iyabo Obasanjo fẹ́ Oluwafolajimi Akeem Bello ní oṣù kẹsàn-án, ọdún 1999. Àwọn tọkọtaya náà pìnyà lẹ́hìn tí Ọbásanjọ́ fi ẹ̀sùn ìkọsílẹ̀ ní ọjọ́ ọ̀kàn-dín-lógún oṣù kárùn-ún, ọdún 2003. Àwọn méjèèjì ní ọmọ kan; Jimi Bello tí a bí ní ọjọ́ ọ̀kàn oṣù kìíní, ọdún 2000 ní Chatham County, North Carolina. [4]

Itokasi àtúnṣe

  1. Obi, Rita (29 March 2005). "Obasanjo's first love". The Sun News Online (The Sun Publishing). http://www.sunnewsonline.com/webpages/features/womanofthesun/2005/mar/29/womanofthesun-29-03-2005-001.htm. 
  2. "Iyabo Obasanjo lies low - The Nation Newspaper". thenationonlineng.net. Retrieved 2022-02-22. 
  3. "Profile". Iyabo 4 Senate. Archived from the original on 19 December 2007. Retrieved 22 December 2007. 
  4. Staff, Daily Post (2011-12-02). "Iyabo Obasanjo’s Ex-Husband Marries Again". Daily Post Nigeria (in Èdè Gẹ̀ẹ́sì). Retrieved 2021-05-25.