Kẹ́mi Adésọyè jẹ́ Òǹkọ̀tàn tí ó kọ gbajú-gbajà eré The Figurine. Ó sì tún ti kọ ọ̀pọ̀lọpọ̀ eré onípele lórí ẹ̀rọ amóhùn-máwòrán bí Tinsel.

Kemi Adesoye
Ọjọ́ìbíOlúwakẹ́mi Adésọyè
Kaduna, Ìpínlè Kaduna,
Orílẹ̀-èdèNigerian
Iṣẹ́screenwriter
Ìgbà iṣẹ́1998–present

Ìbẹ̀rẹ̀ ayé àti ẹ̀kọ́ rè àtúnṣe

Wọ́n bí Adésọyè ní Ìpínlẹ̀ Kwara, ni won to ni Ipinle Kaduna.[1][2] She is the last of four children.[3]

Adésọyè fẹ́ràn láti máa wo àwọn eré bíi eré apanilẹ́rìín, eré adẹ́rùbani, eré oníṣe àti àwọn eré onípele àtìgbà dégbà lóriṣiríṣi. Gẹ́gẹ́ bí akẹ̣́kọ́ nínụ́ ìmọ̀ Architecture ní ilé-ẹ̀kọ́ Yunifásitì. Nígbà tí ó wà ní ọmọ akẹ́kọ́, ìfẹ́ tí ó ní sí ìtàn kíkọ ni ó mu kí ó ṣalábàápàdé ìwé kan tí àkọ́lé rẹ̀ ń jẹ́ "The Elements of Script Writing" tí Irwin R. Blacker kọ. [1][2] Lásìkò yí, kò tíì mọ̀ wípé wọ́n lè fi ìtàn kíkọ ṣe iṣẹ́ oòjọ́ ẹni. Ó lọ sí ilé-ẹ̀kọ́ Federal University of Technology, Minna, ní Ìpínlẹ̀ Niger láti kẹ́kọ̀ọ́ gboyè ìkejì nínú ìmọ̀.[2] Nígbà tí ó bẹ̀rẹ̀ ìwẹ́ kíkọ. Oríṣiríṣi ìpènijà ni ó kojú látàrí àìsí ilé-ẹ̀kọ́ tí ó ń kọ́ni nípa ìtàn kíkọ nígbà náà.[2]Lẹ́yìn tí ó ṣàkíyèsí ìfẹ̣́ rẹ̀ sí ìtàn kíkọ ni ó bá bẹ̀rẹ̀ sí ní kọ́ nípa bí a ṣe ń kọ ìtàn àpilẹ̀kọ ní orí ẹ̀rọ ayélujára, tí ó sì tún lọ kọ́ nípa bí a ṣe ń kọ nípa ìtàn àpilẹ̀kọ ní New York Film Academy ní orílẹ̀-èdè Amẹ́ríkà.[3]

Iṣẹ́ rẹ̀ àtúnṣe

Lẹ́yìn tí Adésọyè jáde nílé ẹ̀kọ́ rẹ̀, ó ṣiṣẹ́ ní ilé iṣẹ́ rédíò fún bí ọdụ́n márùn ún.[3] O kọ ìwé àkọ́kọ́ rẹ̀ ní ọdún 1998. Ó lọ sí ibi ìdánilẹ́kọ̀ọ́ ti IFBA International Film and Broadcast Academy, níbi tí ó ti kọ́kọ́ mọ̀ nípa iṣẹ́ àkànṣe tí wọ́n pè ní "New Directions" tí MNet ṣagbátẹrù rẹ̀. Lásìkò yí, ilé-iṣẹ́ yí ń wá ẹni tí ó lè kọ ìtàn ṣókí fún wọn, ó sì kọ ìtàn kékeré kan fún wọn tí ó pè ní "The Special Gele". Wọ́n mú ìwé ìtàn rẹ̀, lóòtọ́ kò gbébá orókè nínú ìdíje yí, àmọ́ ó ní ìfọ̀kànblalẹ̀ wípé ọjọ́ ọ̀la rẹ̀ dára. Ó kópa nínụ́ ìdíje yí ní ọdún méjì lẹ́yìn , ó sì jáwé olúborí nínú ìdíje náà lér\ léra. Wọ́n si ya eré náà sínú sinimá àgbéléwò. [2][4]

Eré yí ni ó fún Adésọyè ní ànfàní láti bá àwọn jànkàn jànkàn nídí iṣẹ́ sinimá bí Amaka Igwe pàdé. Lẹ́yìn èyí, ó di òǹkọ̀tàn fún ilé-iṣẹ́ DStv, tí ó sì ń kọ àwọn ìtàn eré bí Doctors Quarters. Lẹ́yìn ò rẹyìn, ó ṣalábàpàdé gbajú gbajà olùgbéréjáde Kúnlé Afọláyan, ó kọ eré abanilẹ́rù The Figurine fún tí eré náà sì gbà ọ̀pọ̀lọpọ̀ àmì-ẹ̀yẹ bí Africa Movie Academy Awards lẹ̣́yìn tí wọ́n gbe jáde tán.[2] Látàrí àṣeyọrí eré The Figurine, Adésọyè di ẹni ayé ń fẹ́ pàá pàá jùlọ ní àwùjọ Nollywood gẹ́gẹ́ bị òǹkọ̀wé. Ó tún ti kọ oríṣiríṣi ìtàn onípele àtìgbàdégbà bii: Edge of Paradise, Tinsel, Hotel Majestic, àti àwọn oríṣiríṣi eré mìíràn bí Phone Swap.[2]

Àwọn àṣàyàn eré rẹ̀ àtúnṣe

Eré sinimá àtúnṣe

  • Fifty (2015)
  • New Horizons (Short) (2014)
  • African Metropolis (2013)
  • The Line-Up (Short) (2013)
  • Phone Swap (2012)
  • The Figurine (2009)
  • Prize Maze

Eré orí amóhùnmạ́wòrán àtúnṣe

  • Hotel Majestic (2015-2016)
  • Shuga - season 3 (2013)
  • Tinsel (2008–present)
  • Edge of Paradise (2006-)
  • Doctors' Quarters (2005-2006)

Àwọn àmì-ẹ̀yẹ àti Ìdánimọ̀ rẹ̀ àtúnṣe

Year Award Category Work Result
2012 2012 Best of Nollywood Awards Screenplay of the Year Phone Swap Wọ́n pèé
2013 2013 Nollywood Movies Awards Best Original Screenplay Phone Swap Gbàá
2013 Golden Icons Academy Movie Awards Best Original Screenplay Phone Swap Wọ́n pèé

Àwọn Ìtọ́kasí àtúnṣe

  1. 1.0 1.1 Iwuala, Amarachukwu (25 June 2015). ""Writers Should Learn To Let Go" – Kemi Adesoye". 360nobs.com. Retrieved 24 June 2016. 
  2. 2.0 2.1 2.2 2.3 2.4 2.5 2.6 Njoku, Benjamin (25 April 2015). "‘My story as a screenplay writer’ – Kemi Adesoye". Vanguard. Retrieved 24 June 2016. 
  3. 3.0 3.1 3.2 Oluwadahunsi, Olawale (29 July 2015). "ARTISTE UNCENSORED: Good story is like well-designed building –Kemi Adesoye". National Mirror. Archived from the original on 12 August 2016. Retrieved 24 June 2016. 
  4. "How I Wrote Figurine – Kemi Adesoye". Top Celebrities Nigeria. Archived from the original on 18 August 2016. Retrieved 24 June 2016. 

Ìtàkùn Ìjásóde àtúnṣe

Àdàkọ:Authority control