Túndé Ọládiméjì jẹ́ onífíìmù-ìfiṣerántí, òṣeré, olùdarí-eré àti àtọkún orí tẹlifíṣàn ọmọ orílẹ́-èdè Nàìjíríà. Aṣáájú ni nínú àwọn onífíìmù-ìfiṣèrántí ní èdè abínibí ní Nàìjíríà. Òun ní olùdarí Aàjírebí, ètò òwúrọ̀ tí wọ́n ṣe àfihàn rẹ́ lórí Africa Magic Yorùbá.

Ìbẹ̀rẹ̀ ayé àti iṣẹ́ rẹ̀ àtúnṣe

Wọ́n bí Ọládiméjì ní ìlú Ìsẹ́yìn, Ìpínlẹ̀ Ọ̀yọ́, Nàìjíríà. Olùkọ́ ní ìyá rẹ̀, tí bàbá rẹ̀ sì jẹ́ wọ̀nlẹ̀-wọ̀nlẹ̀. Ó bẹ̀rẹ̀ iṣẹ́ fíìmù ṣíṣe ní Yunifásítì Ìbàdàn níbi tí ó ti kẹ́kọ̀ọ́ gboyè tí ó sì jẹ́ akọ́ọ̀wọ́rìn olótùú fíìmù àkọ́kọ́ rẹ̀, ìwé olóògbé Ọládẹ̀jọ Òkédìjí tí ó lọ ní 1972 tí àkòrí rẹ̀ jẹ́ Àgbàlagbà Akàn tí ó fi ojú rẹ̀ mọlẹ́.

Ó kó ipa gbòógì nínú Bọ̀rọ̀kìní, eré orí-ìtàgé kúkúrú orí tẹlifíṣàn ó sì kópa olù eré nínú fíìmù Akékaka, fíìmù tí Jayé Kútì gbé jáde ti o se àfihàn Fẹ́mi Adébáyọ̀, Mercy Aigbe àti Ẹ̀bùn Olóyèdé Ọlá-Ìyá Bákan náà ni ó jẹ́ amúgbálẹ́gbẹ̀ẹ́ olótùú Amstel. Malta Box Office sáà karùn-ún àti olùdarí Aàjírebí. Ó ṣe àtọkún Àràḿbarà ó sì jẹ́ akọ́ọ̀wọ́rìn olùdarí Ẹlẹ́yinjú àánú, Àràḿbarà.[1]

Ọládiméjì ní olótùú Àwọn Ètò ìfiṣèrántí Àjogúnbá Yorùbá (Yorùbá Heritage Documentary Series). Wọ́n yàn Ìbàdàn ọkàn lára àwọn ètò ìfiṣèrántí nínú ìpele ìfiṣèrántí tí ó peregede jù ní àmì-ẹ̀yẹ Africa Magic Viewer's Choice 2020. Àwọn  ìfiṣèrántí mìíràn nínú ètò ni Èkó Àkéte, Abẹ́òkúta ilẹ̀ Ẹ̀gbá, Ifẹ̀ Oòyè àti Òṣogbo Òròkí.[2]

Àwọn itọ́ka sí àtúnṣe

  1. "Meet Tunde Oladimeji, The AMVCA Nominee Who's Determined To Keep Telling Nigerian Stories". Opera News. 2020-03-17. Archived from the original on 2021-10-05. Retrieved 2021-09-29. 
  2. "Being nominated for AMVCA is an achievement —Oladimeji". Tribune Online. 2020-02-23. Retrieved 2021-09-29.