Ìjẹ̀bú-Òde

ẹkà ìjọba ìbílẹ̀ ti Nàìjíríà
(Àtúnjúwe láti Ijebu Ode)

Ìjẹ̀bú-Òde jẹ́ ìlú tó gbajúmọ̀ nílẹ̀ YorùbáÌpínlẹ̀ Ògùn lápá ìwọ̀-oòrùn orílẹ̀-èdè Nàìjíríà.[1]. Ọba Awùjalẹ̀ ni orúkọ Ọba alạ́dé tí wọ́n fi ń jẹ ní Ìjẹ̀bú-Òde. Ọba Sikiru Kayode Adetona ni ó wà lórí ìtẹ́ lọ́wọ́ ní ìlú Ìjẹ̀bú-Òde.[2]

Ijebu-Ode
Aàfin ọba Ìjẹ̀bú Òde
Aàfin ọba Ìjẹ̀bú Òde
Ijebu-Ode is located in Nigeria
Ijebu-Ode
Ijebu-Ode
Coordinates: 6°49′15″N 3°55′15″E / 6.82083°N 3.92083°E / 6.82083; 3.92083
Country Nigeria
StateOgun
Local Government Areas of NigeriaIjebu-Ode
Government
 • TypeDemocratic
 • AwujaleOba Sikiru Kayode Adetona, Ogbagba Agbotewole II
 • Local Government ChairmanEmilola Gazal Babatunde (APC)
Area
 • Total192 km2 (74 sq mi)
Population
 (2006 Census)
 • Total222,653
Time zoneUTC+1 (WAT)
3-digit postal code prefix
120
Area code(s)120101
National languageYorùbá
Lua error in Module:Mapframe at line 289: attempt to perform arithmetic on local 'lat_d' (a nil value).

Ìtàn ìṣẹ̀dálẹ̀ Ìjẹ̀bú-Òde àtúnṣe

Orísìírísìí ni ìtàn tí à ń gbó nípa ìsèdá ìjèbú Òde. Sùgbón èyí tí ó wó pò jù nínú àwon ìtàn náà ni mo ménu bà yìí; Alárè fi omobìnrin rè kan Gbórowó, fún Odùduwà láti fi se aya. Léhìn èyí, ó gba ònà Ìseri dé Ìbesè, títí ó fi dúró ní Ìjèbú-Òde. Ajèbú àti Olóde jé lára àwon àtèlé Alárè. Fún isé ribiribi won fún ìlú ni a se so Ibùdó náà lórúko won - Ajèbú-Olóde. Àpèjá orúko yìí ni ó di Ìjèbú-Òde lónìí yìí.[3]

Léhìn Alárè ni Lúwà (OLÙ-ÌWÀ) náà dé. Òun náà gba ònà Ilé-Ifè, ó sì yà kí Odùduwà. Lúwà àti Àlárẹ̀ bí ọmọkùnrin kọ̀ọ̀kan. Osi ni ọmọ Lúwà; Eginrin sì ni ọmọ Alárẹ̀. Ní àsìkò yìí. Ọṣìn tàbí Ọlọ́jà ni à ń pe Olórí Ìjẹ̀bú-Òde.[4]

Èdè àìyédè bẹ́ sílẹ̀ láàárín Alárẹ̀ àti Lúwà lórí, i ẹni tí yóò jẹ ọlọ́jà. Nígbà tí wọ́n tọ Ìfá lọ lórí ọ̀rọ̀ yìí, ó fí yé wọn pé ẹni tí yóò jẹ olórí kòì tíì dè!.

Kò pẹ́ kò jìnnà, lẹ́hìn ikú Alárẹ̀ àti Lúwà, ni àjèjì kan tí o múrá pàpà-rẹrẹ wọ̀lú. Ọ̀nà Oǹdó ni àjèji yíí gbà wọ ìlú. Kò pẹ́, ìròhìn ti tàn ká pé àjìji kán fẹ́ gbọ́gun wọ̀lú. Èyí ni ó mú Apèbí (Olóyè pàtàkì kan ní ibùdó yìí) lọ báa bóyá ijà ni ó bá wá ní tòótọ́. Àjèjì yìí kò fèsì lọ báa bóyá ijà ni ó bá wá ní tòótọ́. Àjèjì yìí kò fèsì ju pé “Ìjà dà?. láti fi hàn pé òun kò bá ogun wá. Àjèjì náà fi yé wọ́n pé Ògbòrògánńdá-Ajogun ni orúkọ òun. Ó jẹ́ ọmọ Gbórówó tí í ṣe ọmọbìnrin Alárẹ̀ tí ó fún Odùduwà fẹ́ ní Ilé-Ifẹ̀, Ipasẹ̀ àwọn ẹbí ìyáa rẹ̀ ni Ògbòrògánńdà tọ̀ wá, lẹ́hìn ikú bàbá rẹ̀. Títí di òní, àdúgbò tí Apèbí tí pàdé Ògbòrògánńdà ni à ń pè ní ÌJÀDÀ.

Àpàbí lọ fi tó olóyè àgbà Jaginrìn tí ó rán an níṣẹ́ pé ọwọ́ ẹ̀rọ̀ ni àjèjì náà mú wá. Nígbà tí Jaginrìn bi Apèbí ibi tí àjèjì náà wà, Apèbí dáhùn pé “Ọba-ńníta” (Ọba wà ní ìta) nítorí ipò Ọ́ba ni ó rí i pé ó yẹ ẹni pàtàkì bí i tí Ògbòrògbánnńdà-Ajogun. Láti ìgbà yìí ni a tí mọ Ògbòrògánńdà ní Ọbańníta, tí àjápè rẹ̀ di Ọbańta di òní. Agbègbè tí Ọníṣeémù ti lẹ́ ọ̀sà lọ tí a fún Ògbòrògánńdà láti máa gbé ni ó júwe pé” ó tóó ró”- (Ibí yìí) tó láti dúró sí) ni à ń pè ní Ìtóòró di òní. Àdúgbò yìí ni a ṣe ọ̀wọ́n kan sí ní ìrántí Ọbańta, nítorí a kò mọ bí ó ṣe kú. Inú igbó kan ni tòsí Orù-Àwà ni a gbọ́ pé ó rá sí.

Ògbórògbánńdá Ajogun (Ọbańta) gbé Winniadé, ọmọ Osi níyàwó. Ósi yìí, bí a ti mọ̀ ṣáájú jẹ́ ọmọ Lúwà. Ọbáńta sì jẹ́ ọmọ-ọmọ Alárẹ̀. Wọ́n bí ọmọkùnrin kan tí ó ń jẹ Mọnigbùwà. Síbẹ̀ aáwọ́ tí ó wà láàárín Lúwà àti Alárẹ̀ nípa óyè jíjẹ kò í tán láàárín àwọ́n ẹbí méjèèjì.

Láti fi òpin sí aáwọ̀ yìí, àwọn ará ìlú ní kí Monigbùwà, ọmọ Ọbańta, jáde rẹ̀ ti ṣe ní ọjọ́ kìíní. ‘Mọnigbùwà gbà láti ṣe bẹ́ẹ̀. Ó lọ sí ìletò kan tí a mọ̀ sí Òdo, láti ibẹ̀ ní ó sì ti padà wọ ìlú pẹ̀lú ìfọn àti orin. Ọjọ́ yìí ni a gbé adé fún Mọnígbùwà. Oùn ni ó jẹ́ ẹni àkókó ti ó jẹ oyè Awùjalẹ̀ - ‘A-mu-ìjà-ilẹ̀’-èyí ni ẹni tí ó parí ìjá tí ó bá nílẹ̀. Àpápè oyè yìí ni ó di Awùjalẹ̀ dòní yìí. Títí di òní yìí ni ẹnikẹ́ni tí a bá yàn gẹ́gẹ́ bí ọba tuntun gbọ́dọ̀ jáde ní ìlú lọ sí Òdo, kí ó sì wọ ìlú padà gẹ́gẹ́ bí i Mọnigbùwà àti Ọbańta kí ó tó ó gbadé.

Lára àwọn olóyè pàtàkì-pàtàkì ní Ìjẹ̀bú-Òde ni Olísà Ẹgbọ̀, Àgbọ̀n, Kakaǹfò, Jaginrìn àti Lápòẹkùn, tí wọ́n jẹ́ óyè ìdílé. Àwọn oyè bí i Ọ̀gbẹ́ni Ọjà kìí ṣe oyè ìdílé. Àwùjalẹ̀ kọkànléláàádọ́ta ni a gbọ́ pé ó wà lórí oyè báyìí.

Àwọn Ìjẹ̀bú fẹ́ràn láti máa jẹ kókò àti ọ̀jọ̀jọ̀. Wọ́n tún fẹ́ràn lati máa fi ògìrì sí obẹ̀ àti oúnjẹ wọn mìíràn bíi ikọ́kọrẹ́ láti fún un ní adùn àjẹpọ́nmulá.

Ẹ̀sin àtúnṣe

Ẹlẹ́sìn ìbílẹ̀ ni àwọn ènìyàn Ijẹ̀bú Òde ní ìgbà láíláí. Wọ́n máa ń bọ oríṣiríṣi òrìṣà tí a ń bọ ní gbogbo ilẹ̀ Yorùbá bí i Ògún, Ifá, Èsù àti bẹ́ẹ̀ bẹ́ẹ̀ lọ. Àwọn òrìṣà ìbílẹ̀ bíi Agẹmọ, Òrò, àti Obìnrin-Òjòwú wà pẹ̀lú. Lode oní àwọn ẹ̀sìn ìbílẹ̀ wọ̀nyí kò fi bẹ́ẹ̀ ranlẹ̀ bíi ti àtijọ́ mọ́, síbẹ̀ wọ́n ṣì ń bọ wọ́n lójú méjèèjì. Ẹ̀sìn Mùsùlùmí ni ọ̀pọ̀ àwọn ènìyàn Ìjẹ̀bú-Òde ń ṣe báyìí. Mọṣáláṣí kan wà ní àdúgbò Òyìngbò tí ó jẹ́ ọ̀kan nínú mọ́ṣáláṣí tí ó tóbi jù ni apá ìwọ́ oòrùn Afríka.[5]

Àwọn ẹlẹ́sìn àtẹ̀lé Krístì Lóríṣiríṣi náà kò gbẹ́hìn. Àwọn náà pọ̀ ní ìwọ̀nba tiwọn. Àwọn ìjọ Àgùdà tilẹ̀ fi Ìjẹ̀bú Òde ṣe ibùjúkóó fún dáyósíìsì ti ẹkùn Ìjẹ̀bú.

Àwọn Àdúgbò àtúnṣe

1. Àdúgbò: Itaolówájodá Ìtùmò: Àdúgbò yìí ni àwon ìjòyè Oba ìlú yìí tí a ń pè ni olówá tè dí, ti won si ń se ìjoba lórí àwon ènìyàn tó wà ládùgbó yìí

2. Àdúgbò: Olíwòro Ìtùmò: Àdúgbò yìí ni ojúbo òrìsà alá wà tétètélè, Àwon àwòrò òrìsà yìí ni ó te àdúgbò yìí dó.

3. Àdúgbò: Ìdóbì Ìtùmò: Igi obì púpò ni àwon tó te àdúgbò yìí bá nígbà ti wón fé te ìbè dó.

4. Àdúgbò: Ìtaòsù Ìtùmò: Àdúgbò yìí ni ojúbo òrìsà òsù wa. ni tori pe ibí yìí ni wón ti ń bo òrìsà yìí ni wón se ń pe e ni ìta òsù.

5. Àdúgbò: Imèpè Ìtùmò: Igi òpe púpò ni àwon tó te àdúgbò yìí ban i ibi yìí nígbà tí wón fé te ibè dó

6. Àdúgbò: Ayegun Ìtùmò: Àdúgbò yìí ni òkan lára àwon akoni ode to máa ń ye ojó ogun ti awon olóde yòókù bá ti dá síwájú tè dó ìdí niyìí tí won fi ń pe àdúgbò yìí ni Ayegun.

7. Àdúgbò: Ìtalápò Ìtùmò: Awon ounje orisirisi tí a dì sínú àpò bii àgbàdo, ìyo, ni àwon ara àgbègbè máà ń gbé wá si àdúgbò yìí wá lati tà kí ó tó di àdúgbò. Wón si máà ń na ojà ni àdúgbò yìí títí di òní yìí .

8. Àdúgbò: Ìsasà Ìtùmò: Isé ìkokò mímo ni isé àwon to té àdúgbò yìí dó. Díè lára àwon omo omo won si ń se ìsé yìí

9. Àdúgbò: Ìta Òsùgbó Ìtùmò: Àdúgbò yìí ni àwon Olósùgbó ti máà ń se ìpàdé. Níbè ni ilé ìpàdé wón wa, kí ó tó di pé won te ibè dó.

10. Àdúgbò: Ìsesí Ìtùmò: Ibí yìí ni ójúbo osi esi wà télètélè kí o to di pé won te ibè do tí o si dí àdúgbò ojúbo osi yìí si wa níbè títí dònìí.

11. Àdúgbò: Ìta Opó Ìtùmò: Àwon Opó ni won máà ń na ojà yìí ni alaalé. Òríta ti wón ń náà yìí ni o di adúgbò, ti wón si ń pe ni ìtà opó. Wón si máà ń ná ojà alé ni àdúgbò yìí títí dònìí

12. Àdúgbò: Molípáà Ìtùmò: Okunrin kan tó mú opà dání ló te apá ibí yìí dó. Ìtàn so fún wa pé àpá ase Oba ìlú ibòmíìràn ló mu dàni nígbà tí o ń bo, àwon kan tilè so pé Àremo oba ìlú náà ni. Nígbà tí o, fé te àdúgbò náà do ó mú òpá yìí dá ni, Ìdí niyìí tó fi je pé won ń je oba ni àdúgbò náà títí di òní yìí

13. Àdúgbò: Ìtóòrò Ìtùmò: Ìtàn so fún wa pé omi nigbogbo àdúgbò yìí teletélè kí ó to dí pe wón te ibè do. Okunrin akoni ti a ń pè ni òró ni o pé ofò tí ó sì le omi náà lo. Ìdí nìyìí ti a fi ń pé àdúgbò náà ni Ìtóòró.

14. Àdúgbò: Olóde Ìtùmò: Ibí yìí ni òkan lára àwon akoni tó te ìlú yii dó kokó dúró si kó tó dip é ó wo àárin ìlú lo. Nígbà ti ijà dé láàrin òun àti àwon tí wón fo wo ìlú yìí, o bínú pàdà si ibi yìí o si wolè. Ìdí niyìí tí wón fi ń pe àdúgbò naa ni Olóde. Oórì okùnrin yìí si wà níbè títí dòníì.

15. Àdúgbò: Odò Èsà Ìtùmò: Eégún kan ti won ń pè ni obrinrin ojòwú ní o te ibí yìí dó. Èégún Odoodún ni eégún máà ń jáde ni àdúgbò yìí títí donii. Ìdí igi ìrókò ni won fi se ojúbo eégún yìí Igi ìrókò yii wà níbè títí dónì yìí.

16. Àdúgbò: Ìdépo Ìtùmò: Isé epo ni àwon to te àdúgbò yìí yàn láàyò léyìn tí wón ti dó síbè. Bí o tilè jé pé won kò se ise epó níbè mó, won si ń ná ojà epo níbè titi dò níí.

17. Àdúgbò: Fìdípòtè Ìtùmò: Lára àwon ìjòyè oba Gbélébùwà àkókó tí won kò fara mo on pé kí wón pa Oba náà ni won wa te àdúgbò yìí dó léyìn ti wón kúrò ni ààfún.

18. Àdúgbò: Apèbi Ìtùmò: Oríta yìí ni àwon ìjoyè Oba Gbétebùwá àkókó péjo sí láti bi ara won ohun ti o ye kí àwon se fún oba náà.

19. Àdúgbò: Ìdéwòn Ìtùmò: Ìtàn so gún wa pé nígbà tí wín fe te ibí yìí dó, wón bá òrìsà kan níbè tó dé adé sórí tó sì fi èwòn onírin se ileke owó àti tí esè. Ìdí ni yìí ti à fi máà ń yan Oba láti ìdílé enití ó te àdúgbò náà dó. Ìdílè yìí náà tílè ni ààfún tí a ń pè ni ààfin Òba ìdéwon.

20. Àdúgbò: Ìta Àfín Ìtùmò: Ìtàn so fún wa pé bí ó tilè jé pé èrúktí o té àdúgbò yìí do kii se àfín, sùgbón gbogbo àwon omo tí won bi láti ìdílè enití o te àdúgbò náà do je àfín. Nígbà ti won lo bi ifá wo, Ifá ni ki won máà bo Obàtálá ni ìdílé náà, láti ìgbà náà lo ni won ti ń bo Obàtálá ni ìdílè yìí. Ti o bad i àsìkò odún òrìsà yìí, àríyá ni fún gbogbo àwon omo àdúgbò yìí àti fún ìlú pàápàá.


Àwọn Ìtọ́ka sí àtúnṣe

  • C.O. Onanuga (1981), ‘Ìlú Ìjèbú-Òde’, láti inú ‘Odún Òrìsà Agemo ní Agbègbè Ìjèbú-Òde.’, Àpilèko fún Oyè Bíeè, DALL. OAU, Ifè, Nigeria, ojú-ìwé 3-6
  1. "Ijebu-Ode - Nigeria". Encyclopedia Britannica. Retrieved 2019-09-21. 
  2. "Seven interesting facts about Awujale of Ijebu at 85". The Nation Newspaper. 2019-05-10. Retrieved 2019-09-21. 
  3. Oduwobi, Tunde (2014-05-13). "Oral Historical Traditions and Political Integration in Ijebu - History in Africa". History in Africa 27: 249–259. doi:10.2307/3172116. ISSN 0361-5413. https://www.cambridge.org/core/journals/history-in-africa/article/abs/oral-historical-traditions-and-political-integration-in-ijebu/60562D6100AF7163C1AC8D7E2E9F3FB0. Retrieved 2021-07-20. 
  4. "Ijebu-Ode Town in Ogun Nigeria Guide". NigeriaGalleria. Retrieved 2021-07-20. 
  5. "Aiyepe Central Mosque, Ijebu Ode, Aiyepe, Nigeria, National Park, state Ogun". NG.infoaboutcompanies.com. Retrieved 2021-07-20.