Loyola College, Ibadan (LCI) jẹ́ Ilé-ẹ̀kọ́ ìjọba èyí tí ó wà fún àwọn àwọn ọmọkùnrin ní Ìpínlẹ̀ Ọ̀yọ́ Oyo State, ní orílẹ̀ èdè Nàìjíríà Nigeria. Èyí tí àwọn òjíṣẹ́ ìsìn Kátólíìkì Catholic Missionary dá sílẹ̀ ní ọdún 1954. Ó wà láàárín òpópónà Ifẹ̀ àtijọ́, agbègbè Agodi ní Ìbàdàn Ibadan. Láti ìdásílẹ̀ rẹ̀, Ilé-ẹ̀kọ́ náà tí pèsè àwọn onímọ̀ tí wọ́n dáńtọ ní àwọn ààyè bíi ti ìmọ̀ ìṣègùn àwọn òyìnbó,

Loyola College, Ibadan
Loyala college.png

Veritas (Truth)
Location
Ibadan, Oyo State, Nàìjíríà
Information
Type Public
Established 1954; ọdún 70 sẹ́yìn (1954)
Gender Boys
Website

mọ̀ìẹ̀

iòọ-ẹrọìṣèlún,ìròyìnuìkàn-sárá-ìlú à meàia aàyè ńlá-ńlá ọn oojọ mìíràn. [1]

Àwọn ènìyàn jà-ǹ-kàn jà-ǹ-kàn tí wọ́n jáde níbẹ̀ àtúnṣe

Ilé-ẹ̀kọ́ Loyola College ti pèsè àwọn onírúurú ènìyàn tí wọ́n jẹ́ jà-ǹ-kàn jà-ǹ-kàn ní àwọn ààyè oríṣiríṣi, lára wọn ni a ti rí :

  • Lam Adesina, ẹni tí ó ti fi ìgbà kan rí jẹ́ gómìnà Ìpínlẹ̀ Ọ̀yọ́ Oyo State
  • Oluwarotimi Odunayo Akeredolu, ẹni tí ó jẹ́ àgbà agbẹjọ́rò ní orílẹ̀ èdè Nàìjíríà Senior Advocate of Nigeria (SAN) tí ó sì tún jẹ gómìnà ní Ìpínlẹ̀ Òǹdó Ondo State.
  • Dele Bakare, onímọ̀ ẹ̀rọ ayélujára àti olókoowò
  • Raymond Dokpesi, oníṣòwò ètò ayélujára ìkàn-sárá-ìlú
  • Akin Fayomi, aṣojú ìjọba
  • Oluseun Onigbinde, olókoowò
  • Lawson Oyekan, (ceramic sculptor)
  • Professor Patrick Utomi, ògbóǹtarìgì ọrọ̀-ajé àti ẹni tí ó ti fi ìgbà kan díje dupò Ààrẹ orílẹ̀ èdè Nàìjíríà
  • Oba Adeyeye Enitan Ogunwusi, Ọba Ilé-Ifẹ̀
  • Ekpo Una Owo Nta, Amòfin, alága àjọ olómìnira tó ń rí sí ìwà ìbàjẹ́ àti àwọn ìwà tí ó jọ mọ́ ọn mìíràn (ICPC)
  • Olumide Oyedeji, agbábọ́ọ̀lù aláfọwọ́ jù sáwọ̀n (basketballer) tí ó sì ṣe takuntakun nínú eré bọ́ọ̀lù ti NBA ní US, tí ó sì tún jẹ́ olórí fún àwọn agbábọ́ọ̀lù aláfọwọ́ jù sáwọ̀n ti orílẹ̀ èdè Nàìjíríà (D'Tigers) nínú eré Olympics ọdún 2012.

Àwọn ìtọ́kasí àtúnṣe

External links àtúnṣe

Coordinates: 7°23′27″N 3°55′32″E / 7.39086°N 3.92569°E / 7.39086; 3.92569

Àdàkọ:Nigeria-school-stub